< Psalms 73 >

1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Psaume d'Asaph. Oui, Dieu est bon pour Israël, Pour ceux qui ont le coeur pur.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
Cependant, mes pieds ont failli broncher: Il s'en est fallu de peu que j'aie glissé!
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
En effet, j'ai porté envie aux orgueilleux, Quand j'ai vu la prospérité des méchants!
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Car ils sont exempts de souffrance; Leur corps demeure vigoureux et robuste.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
Ils n'ont aucune part aux peines des mortels; Ils ne sont point frappés avec les autres humains.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
C'est pourquoi, ils se parent d'orgueil comme d'un collier; La violence les couvre comme un vêtement.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Ils sont bouffis de graisse, pleins d'iniquité, Et leur coeur déborde de mauvaises pensées.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
Ils ricanent, ils se vantent méchamment de leurs violences; Leurs paroles sont hautaines.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Leur bouche s'élève contre le ciel, Et leur langue sème la calomnie sur la terre.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Aussi attirent-ils à leur cause une foule de gens Qui boivent avidement leurs paroles,
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
Et qui disent: «Comment le Dieu fort pourrait-il savoir? Comment le Très-Haut connaîtrait-il?»
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Tels sont les méchants: Toujours heureux, ils amassent des richesses.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
C'est donc en vain que j'ai gardé mon coeur pur, Et que j'ai lavé mes mains dans l'innocence;
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
Car je suis frappé tous les jours, Et le châtiment tombe chaque matin sur moi.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Si j'avais dit: «Je parlerai comme eux» — Alors, j'aurais été infidèle à la race de tes enfants.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
J'ai donc cherché à comprendre ces choses; Mais la tâche a été trop pénible pour moi,
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
Jusqu'au moment où je suis entré Dans les sanctuaires du Dieu fort, Et où j'ai fait attention à la fin de ces gens-là.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Oui, tu les mets sur un terrain glissant; Tu les fais tomber, et ils s'écroulent!
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
Comme ils sont détruits en un moment. Enlevés et consumés par une destruction soudaine!
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Tel un songe, quand on s'éveille. Ainsi, Seigneur, quand tu te lèves, Tu les dissipes comme de vains fantômes.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Quand l'amertume remplissait mon coeur, Et que je me tourmentais en moi-même,
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
Alors j'étais sans raison et sans intelligence; J'étais à tes yeux comme un animal stupide.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
Cependant, je resterai toujours avec toi: Tu m'as pris par la main droite.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Tu me guideras par ta sagesse. Et puis, tu m'introduiras dans la gloire.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Quel autre que toi ai-je au ciel? Sur la terre aussi, je ne prends plaisir qu'en toi.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Quand même ma chair et mon coeur seraient consumés, Dieu est le rocher de mon coeur, et mon partage pour toujours.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Oui, ceux qui s'éloignent de toi périront; Tu détruis tous ceux qui se détournent de toi.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
Pour moi, m'approcher de Dieu, c'est mon bonheur; Je mets ma confiance dans le Seigneur, l'Éternel, Afin de raconter toutes ses oeuvres.

< Psalms 73 >