< Psalms 73 >

1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Un psaume d'Asaph. Certes, Dieu est bon pour Israël, à ceux qui ont le cœur pur.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
Mais quant à moi, mes pieds étaient presque partis. Mes pas avaient presque glissé.
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
Car j'étais envieux des arrogants, quand j'ai vu la prospérité des méchants.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Car il n'y a pas de lutte dans leur mort, mais leur force est ferme.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
Ils sont libérés des fardeaux des hommes, ils ne sont pas non plus frappés comme les autres hommes.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
C'est pourquoi l'orgueil est comme un collier à leur cou. La violence les couvre comme un vêtement.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Leurs yeux sont gonflés de graisse. Leur esprit dépasse les limites de la vanité.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
Ils se moquent et parlent avec méchanceté. Dans leur arrogance, ils menacent d'oppression.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Ils ont placé leur bouche dans les cieux. Leur langue traverse la terre.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
C'est pourquoi leur peuple revient vers eux, et ils boivent des eaux en abondance.
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
Ils disent: « Comment Dieu le sait-il? Y a-t-il de la connaissance dans le Très-Haut? »
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Voici, ce sont les méchants. Étant toujours à l'aise, ils augmentent leurs richesses.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
C'est en vain que j'ai purifié mon cœur, et je me suis lavé les mains en toute innocence,
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
Car toute la journée, j'ai été tourmenté, et puni chaque matin.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Si j'avais dit: « Je vais parler ainsi », Voici, j'aurais trahi la génération de vos enfants.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
Quand j'ai essayé de comprendre ça, c'était trop douloureux pour moi...
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
jusqu'à ce que j'entre dans le sanctuaire de Dieu, et envisagé leur fin.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Tu les as placés dans des endroits glissants. Vous les jetez à la destruction.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
Comme ils sont soudainement détruits! Ils sont complètement emportés par la terreur.
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Comme un rêve quand on se réveille, alors, Seigneur, à votre réveil, vous mépriserez leurs fantasmes.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Car mon âme était affligée. J'étais aigri dans mon cœur.
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
J'étais tellement insensé et ignorant. J'étais une bête brute avant toi.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
Néanmoins, je suis continuellement avec vous. Tu as tenu ma main droite.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Tu me guideras par tes conseils, et ensuite me recevoir dans la gloire.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Qui ai-je dans le ciel? Il n'y a personne sur terre que je désire en dehors de toi.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Ma chair et mon cœur sont défaillants, mais Dieu est la force de mon cœur et mon partage pour toujours.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Car voici, ceux qui sont loin de toi périront. Tu as détruit tous ceux qui t'étaient infidèles.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
Mais il est bon pour moi de m'approcher de Dieu. J'ai fait du Seigneur Yahvé mon refuge, pour que je puisse raconter toutes tes œuvres.

< Psalms 73 >