< Psalms 73 >

1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Aasafin virsi. Totisesti, Jumala on hyvä Israelille, niille, joilla on puhdas sydän.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
Mutta minun jalkani olivat vähällä kompastua, askeleeni olivat aivan liukahtaa.
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
Sillä minussa nousi kateus ylvästelijöitä kohtaan, kun minä näin jumalattomien menestyvän.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Sillä he ovat vaivoista vapaat kuolemaansa asti, he ovat voimakkaat ja lihavat.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
Eivät he koe muitten kuolevaisten tuskia, eikä heitä vaivata niinkuin muita ihmisiä.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
Sentähden on ylpeys heillä kaulakoristeena, väkivalta on puku, joka heidät verhoaa.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Heidän silmänsä pullistuvat ulos heidän lihavuudestaan, heidän sydämensä kuvittelut kulkevat valtoimina.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
He pilkkaavat ja puhuvat väkivallan puheita pahuudessansa, he puhuvat kuin korkeuksista.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Heidän suunsa tavoittelee taivasta, ja heidän kielensä kulkee pitkin maata.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Sentähden heidän kansansa liittyy heihin ja särpii vettä kyllälti.
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
Ja he sanovat: "Kuinka Jumala sen tietäisi, onko tietoa Korkeimmalla?"
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Katso, nämä ovat jumalattomat; kuitenkin he elävät ainaisessa rauhassa ja rikastuvat yhäti.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
Turhaan minä olen pitänyt sydämeni puhtaana ja pessyt käteni viattomuudessa:
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
minua vaivataan joka aika, ja minä saan joka aamu kuritusta.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Jos olisin sanonut: "Noin minäkin puhun", katso, niin minä olisin ollut petollinen koko sinun lastesi sukua kohtaan.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
Minä mietin päästäkseni tästä selvyyteen; mutta se oli minulle ylen vaikeata,
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
kunnes minä pääsin sisälle Jumalan pyhiin salaisuuksiin ja käsitin, mikä heidän loppunsa on oleva.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Totisesti, sinä panet heidät liukkaalle, perikatoon sinä heidät syökset.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
Kuinka he joutuvatkaan äkisti turmioon! He hukkuvat, heidän loppunsa on kauhistava.
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Niinkuin unen käy herätessä, niin sinä, Herra, kun heräjät, heidän valhekuvansa hylkäät.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Kun minun sydämeni katkeroitui ja minun munaskuihini pisti,
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
silloin minä olin järjetön enkä mitään älynnyt, olin sinun edessäsi kuin nauta.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
Kuitenkin minä pysyn alati sinun tykönäsi, sinä pidät minua kiinni oikeasta kädestäni.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Sinä talutat minua neuvosi mukaan ja korjaat minut viimein kunniaan.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Ketä muuta minulla olisi taivaassa! Ja kun sinä olet minun kanssani, en minä mistään maan päällä huoli.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Vaikka minun ruumiini ja sieluni nääntyisi, Jumala on minun sydämeni kallio ja minun osani iankaikkisesti.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Sillä katso, jotka sinusta eriävät, ne hukkuvat, sinä tuhoat kaikki, jotka haureudessa sinusta luopuvat.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
Mutta minun onneni on olla Jumalaa lähellä, minä panen turvani Herraan, Herraan, kertoakseni kaikkia sinun tekojasi.

< Psalms 73 >