< Psalms 73 >
1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
A Psalm of Asaph. Truly God [is] good to Israel, [even] to such as are of a clean heart.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
But as for me, my feet were almost gone; my steps had well nigh slipped.
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
For I was envious at the foolish, [when] I saw the prosperity of the wicked.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
For [there are] no bands in their death: but their strength [is] firm.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
They [are] not in trouble [as other] men; neither are they afflicted like [other] men.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
Therefore pride encompasseth them as a chain; violence covereth them [as] a garment.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Their eyes stand out with fatness: they have more than heart could wish.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
They are corrupt, and speak wickedly [concerning] oppression: they speak loftily.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
They set their mouth against the heavens, and their tongue walketh through the earth.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Therefore his people return hither: and waters of a full [cup] are wrung out to them.
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
And they say, How doth God know? and is there knowledge in the Most High?
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Behold, these [are] the ungodly, who prosper in the world; they increase [in] riches.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
Verily I have cleansed my heart [in] vain, and washed my hands in innocence.
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
For all the day long have I been afflicted, and chastened every morning.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
If I say, I will speak thus; behold, I should offend [against] the generation of thy children.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
When I thought to know this, it [was] too painful for me;
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
Until I went into the sanctuary of God; [then] I understood their end.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Surely thou didst set them in slippery places: thou didst cast them down into destruction.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
How are they [brought] into desolation, as in a moment! they are utterly consumed with terrors.
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
As a dream when [one] awaketh; [so], O LORD, when thou awakest, thou wilt despise their image.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Thus my heart was grieved, and I was pricked in my reins.
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
So foolish [was] I, and ignorant: I was [as] a beast before thee.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
Nevertheless I [am] continually with thee: thou hast held [me] by my right hand.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Thou wilt guide me with thy counsel, and afterward receive me [to] glory.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Whom have I in heaven [but thee]? and [there is] none upon earth [that] I desire besides thee.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
My flesh and my heart faileth: [but] God [is] the strength of my heart, and my portion for ever.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
For lo, they that are far from thee shall perish: thou hast destroyed all them that go astray from thee.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
But [it is] good for me to draw near to God: I have put my trust in the Lord GOD, that I may declare all thy works.