< Psalms 72 >

1 Ti Solomoni. Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run, ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
Psalm dla Salomona. Boże, daj królowi swoje sądy i swoją sprawiedliwość synowi króla;
2 Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo, yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
Będzie sądził twój lud w sprawiedliwości, a twoich ubogich w prawości.
3 Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
Góry przyniosą ludowi pokój, a pagórki sprawiedliwość.
4 Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn yóò gba àwọn ọmọ aláìní; yóò sì fa àwọn aninilára ya.
Będzie sądził ubogich z ludu, wybawi synów potrzebującego, a zgniecie ciemiężyciela.
5 Àwọn òtòṣì àti aláìní yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn, yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
Będą się bać ciebie, póki trwać będzie słońce i księżyc, z pokolenia na pokolenie.
6 Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀, bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
Zstąpi jak deszcz na skoszoną trawę, jak krople deszczu nawadniające ziemię.
7 Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà; títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
Za jego dni zakwitnie sprawiedliwy i [będzie] obfitość pokoju, dopóki księżyc trwa.
8 Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
Będzie panował od morza do morza, od rzeki aż po krańce ziemi.
9 Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
Przed nim upadną mieszkańcy pustyni, a jego wrogowie będą proch lizać.
10 Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù wọn yóò mú ọrẹ wá fún un; àwọn ọba Ṣeba àti Seba wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
Królowie Tarszisz i wysp przyniosą dary, królowie Szeby i Saby złożą daninę.
11 Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
I oddadzą mu pokłon wszyscy królowie; wszystkie narody będą mu służyć.
12 Nítorí yóò gba àwọn aláìní nígbà tí ó bá ń ké, tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
Ocali bowiem ubogiego, gdy zawoła, i nędznego, który nie ma pomocnika.
13 Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
Zmiłuje się nad ubogim i potrzebującym i wybawi dusze nędzarzy.
14 Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
Wybawi ich dusze od podstępu i przemocy, bo ich krew [jest] cenna w jego oczach.
15 Yóò sì pẹ́ ní ayé! A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba. Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
I będzie żył, i dadzą mu złoto z Szeby; nieustannie będą się za niego modlić i codziennie mu błogosławić.
16 Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀; ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
Gdy się zasieje garść zboża w ziemi na szczytach gór, jego plon zaszumi jak Liban, a mieszkańcy miast zakwitną jak polna trawa.
17 Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé; orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó. Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
Jego imię [trwać] będzie na wieki; póki słońce trwa, trwać będzie jego imię; [ludzie] będą błogosławieni w nim, a wszystkie narody nazwą go błogosławionym.
18 Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli, ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
Błogosławiony niech będzie PAN Bóg, Bóg Izraela, który sam jeden czyni cuda.
19 Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé; kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
I błogosławione na wieki jego chwalebne imię; niech cała ziemia będzie napełniona jego chwałą. Amen, amen.
20 Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.
[I tu] się kończą modlitwy Dawida, syna Jessego.

< Psalms 72 >