< Psalms 72 >

1 Ti Solomoni. Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run, ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
Salamontól. Isten, ítéleteidet add a királynak és igazságodat a király fiának;
2 Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo, yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
itélje népedet igazsággal és szegényeidet jog szerint.
3 Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
Teremjenek a hegyek békét a népnek és a halmok igazságot.
4 Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn yóò gba àwọn ọmọ aláìní; yóò sì fa àwọn aninilára ya.
Jogot szerezzen a nép szegényeinek, segítsen a szükölködő fiainak és zúzza szét a fosztogatót.
5 Àwọn òtòṣì àti aláìní yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn, yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
Féljenek téged, a meddig nap van, s a míg hold lesz, nemzedéken, nemzedékeken át.
6 Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀, bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
Szálljon le, mint eső a kaszáló rétre, mint zápor, mely áztatja a földet.
7 Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà; títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
Viruljon napjaiban az igaz, és bőviben legyen béke a hold enyésztéig.
8 Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
És uralkodjék tengertől tengerig s a folyamtól a föld végéig.
9 Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
Előtte térdeljenek a pusztalakók, és ellenségei port nyaldossanak.
10 Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù wọn yóò mú ọrẹ wá fún un; àwọn ọba Ṣeba àti Seba wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
Tarsís és a szigetek királyai ajándékkal adózzanak, Sebá és Szebá királyai adót mutatnak be.
11 Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
És leborúlnak előtte mind a királyok, mind a nemzetek szolgálják őt.
12 Nítorí yóò gba àwọn aláìní nígbà tí ó bá ń ké, tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
Mert megmenti a szűkölködőt, ki esedezik és a szegényt, meg azt, kinek nincsen segítője;
13 Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
szánakozik ügyefogyottan és szűkölködőn és a szűkölködők lelkeit megsegíti;
14 Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
elnyomástól és erőszaktól megváltja lelküket, és drága az ő vérük szemeiben.
15 Yóò sì pẹ́ ní ayé! A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba. Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
Majd föléled s ad neki Sebá aranyából; imádkozik érte mindig, egész nap áldja őt.
16 Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀; ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
Legyen gabonának bősége az országban a hegyek esúcsán, rengjen mint a Libánon a termése és virágozzanak ki a városból, mint a földnek füve.
17 Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé; orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó. Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
Legyen neve örökre, a míg nap lesz, aarjadozzék never és áldják magukat vele, mind a nemzetek boldognak mondják!
18 Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli, ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
Áldva legyen az Örökkévaló, az Isten, lzraél Istene, ki egyedül müvel csodás tetteket!
19 Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé; kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
És áldva legyen dicsőséges neve örökre és teljék meg dicsőségével az egész föld! Ámen és Ámen!
20 Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.
Vége Dávid, Jísaj fia imáinak.

< Psalms 72 >