< Psalms 72 >

1 Ti Solomoni. Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run, ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
A Psalme of Salomon. Give thy iudgements to the King, O God, and thy righteousnesse to the Kings sonne.
2 Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo, yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
Then shall he iudge thy people in righteousnesse, and thy poore with equitie.
3 Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
The mountaines and the hilles shall bring peace to the people by iustice.
4 Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn yóò gba àwọn ọmọ aláìní; yóò sì fa àwọn aninilára ya.
He shall iudge the poore of the people: he shall saue the children of the needie, and shall subdue the oppressor.
5 Àwọn òtòṣì àti aláìní yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn, yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
They shall feare thee as long as the sunne and moone endureth, from generatio to generation.
6 Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀, bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
He shall come downe like the rayne vpon the mowen grasse, and as the showres that water the earth.
7 Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà; títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
In his dayes shall the righteous florish, and abundance of peace shalbe so long as the moone endureth.
8 Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
His dominion shall be also from sea to sea, and from the Riuer vnto the endes of the land.
9 Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
They that dwell in ye wildernes, shall kneele before him, and his enemies shall licke the dust.
10 Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù wọn yóò mú ọrẹ wá fún un; àwọn ọba Ṣeba àti Seba wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
The Kings of Tarshish and of the yles shall bring presents: the Kings of Sheba and Seba shall bring giftes.
11 Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
Yea, all Kings shall worship him: all nations shall serue him.
12 Nítorí yóò gba àwọn aláìní nígbà tí ó bá ń ké, tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
For he shall deliuer the poore when he cryeth: the needie also, and him that hath no helper.
13 Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
He shalbe mercifull to the poore and needie, and shall preserue the soules of the poore.
14 Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
He shall redeeme their soules from deceite and violence, and deare shall their blood be in his sight.
15 Yóò sì pẹ́ ní ayé! A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba. Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
Yea, he shall liue, and vnto him shall they giue of the golde of Sheba: they shall also pray for him continually, and dayly blesse him.
16 Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀; ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
An handfull of corne shall be sowen in the earth, euen in the toppe of the mountaines, and the fruite thereof shall shake like the trees of Lebanon: and the children shall florish out of the citie like the grasse of the earth.
17 Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé; orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó. Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
His name shall be for euer: his name shall indure as long as the sunne: all nations shall blesse him, and be blessed in him.
18 Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli, ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
Blessed be the Lord God, euen the God of Israel, which onely doeth wonderous things.
19 Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé; kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
And blessed be his glorious Name for euer: and let all the earth be filled with his glorie. So be it, euen so be it.
20 Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.
HERE END THE prayers of Dauid, the sonne of Ishai.

< Psalms 72 >