< Psalms 72 >

1 Ti Solomoni. Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run, ọmọ-aládé ni ìwọ fi òdodo rẹ fún.
[Solomon kah] Pathen aw, namah kah laitloeknah te manghai ham, na duengnah khaw manghai capa ham khueh pah.
2 Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo, yóò sì máa fi ẹ̀tọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn tálákà rẹ̀.
Na pilnam te duengnah neh, namah kah mangdaeng rhoek khaw tiktamnah neh lai a tloek pah bitni.
3 Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn àti òkè kéékèèké nípa òdodo.
Tlang rhoek neh som rhoek loh duengnah dongah pilnam ham rhoepnah hang khuen uh saeh.
4 Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn yóò gba àwọn ọmọ aláìní; yóò sì fa àwọn aninilára ya.
Pilnam mangdaeng rhoek te tang sak saeh. Khodaeng ca rhoek te khang saeh lamtah hlang aka hnaemtaek te phop saeh.
5 Àwọn òtòṣì àti aláìní yóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo, níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn, yóò ti pẹ́ tó, láti ìrandíran.
Khomik a om khui neh hla a om khuiah cadilcahma kah cadilcahma loh namah n'rhih uh saeh.
6 Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀, bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀.
Lotul kah khotlan bangla, diklai aka hnim sak mueitui bangla suntla saeh.
7 Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà; títí tí òṣùpá kò fi ní sí mọ́.
Amah tuetang van vaengah hla loh a hmop hlandue ngaimongnah cungkuem neh a dueng la cawn saeh.
8 Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun àti láti odò Eufurate títí dé òpin ayé.
Te vaengah tuitunli lamkah tuitunli due khaw tuiva lamkah diklai khobawt due taemrhai saeh.
9 Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.
Anih hmai ah kohong rhoek loh cungkueng uh saeh lamtah a thunkha rhoek loh laipi laem uh saeh.
10 Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù wọn yóò mú ọrẹ wá fún un; àwọn ọba Ṣeba àti Seba wọn ó mú ẹ̀bùn wá fún un.
Tarshish neh tuikaeng manghai rhoek loh khosaa han tloeng uh saeh. Sheba neh Seba manghai rhoek loh kutdoe neh moe uh saeh.
11 Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un àti gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sìn ín.
Manghai rhoek boeih khaw anih taengah bakop uh saeh. Namtom rhoek boeih loh a taengah thothueng saeh.
12 Nítorí yóò gba àwọn aláìní nígbà tí ó bá ń ké, tálákà àti ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
Khodaeng loh pang tih mangdaeng aka bom a om pawt vaengah anih loh huul saeh.
13 Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní yóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.
Tattloel neh khodaeng te rhen saeh lamtah khodaeng kah hinglu te khang saeh.
14 Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá nítorí ẹ̀jẹ̀ wọn ṣọ̀wọ́n níwájú rẹ̀.
Tattloel neh vawtthoek kah a thii te a mikhmuh ah a phutlo. Te dongah amih kah hinglu te hnaephnapnah kut lamkah neh kuthlahnah khui lamkah tlan pah saeh.
15 Yóò sì pẹ́ ní ayé! A ó sì fún un ní wúrà Ṣeba. Àwọn ènìyàn yóò sì máa gbàdúrà fún un nígbà gbogbo kí a sì bùkún fún un lójoojúmọ́.
A hing van vaengah Sheba kah sui te anih taengah pae saeh. Te phoeiah anih ham thangthui pah saeh lamtah hnin takuem anih te yoethen pae yoeyah saeh.
16 Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀; ní orí òkè ni kí ó máa dàgbà kí èso rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lebanoni yóò máa gbá yìn bí i koríko ilẹ̀.
Khohmuen ah cangpai cangthawt om saeh lamtah, tlang som ah Lebanon thaihtae bangla petpet naep saeh. Khopuei khuiah khaw lohma baelhing bangla khooi saeh.
17 Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé; orúkọ rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọ̀n bí oòrùn yóò ti pẹ́ tó. Wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nípasẹ̀ rẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.
Kumhal ah a ming om saeh. Khomik a om khuiah anih ming te rhoeng rhoe rhoeng saeh. Namtom boeih khaw anih rhang neh a yoethen uh saeh lamtah anih te uem uh saeh.
18 Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli, ẹnìkan ṣoṣo tí ó ń ṣe ohun ìyanu.
Amah rhoerhoe loh khobaerhambae aka saii Israel Pathen, BOEIPA Pathen a yoethen pai saeh.
19 Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé; kí gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.
Amah kah thangpomnah ming khaw kumhal ah a yoethen pai tih, diklai pum he amah thangpomnah loh khuk saeh. Amen phoeiah Amen.
20 Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.
Jesse capa David kah thangthuinah rhoek tah cup coeng.

< Psalms 72 >