< Psalms 71 >

1 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
În tine, DOAMNE, îmi pun încrederea, să nu fiu dat niciodată de rușine!
2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Eliberează-mă în dreptatea ta și lasă-mă să scap, apleacă-ți urechea spre mine și salvează-mă.
3 Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Fii tu locuința mea tare, la care să alerg întotdeauna; ai dat poruncă să mă salvezi, căci tu ești stânca mea și fortăreața mea.
4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
Eliberează-mă, Dumnezeul meu, din mâna celui stricat, din mâna omului nedrept și crud.
5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Căci tu ești speranța mea și încrederea mea Doamne Dumnezeule, din tinerețea mea.
6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
Prin tine am fost sprijinit din pântece, tu ești cel ce m-ai scos din adâncurile mamei mele; lauda mea va fi întotdeauna despre tine.
7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
Sunt de minune pentru mulți; dar tu ești locul meu puternic de scăpare.
8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
Toată ziua să se umple gura mea cu lauda ta și cu onoarea ta.
9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
Nu mă lepăda în timpul bătrâneții; nu mă părăsi când puterea mea încetează.
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
Căci dușmanii mei vorbesc împotriva mea; și cei ce îmi pândesc sufletul se sfătuiesc împreună,
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
Spunând: Dumnezeu l-a părăsit, persecutați-l și luați-l, căci nu este nimeni să îl elibereze.
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
Dumnezeule, nu sta departe de mine; Dumnezeul meu, grăbește-te în ajutorul meu.
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Să fie încurcați și mistuiți potrivnicii sufletului meu; să fie acoperiți cu ocară și dezonoare cei ce îmi caută vătămarea!
14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
Dar voi spera continuu și îți voi aduce tot mai mult laudă.
15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
Toată ziua gura mea va arăta dreptatea ta și salvarea ta, fiindcă nu știu numărul lor.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
Voi merge în puterea Domnului DUMNEZEU, voi aminti despre dreptatea ta, doar a ta.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Dumnezeule, tu m-ai învățat din tinerețea mea și până acum am vestit lucrările tale minunate.
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
Acum de asemenea când sunt bătrân și încărunțit, Dumnezeule, nu mă părăsi; până când voi arăta tăria ta acestei generații și puterea ta fiecăruia ce vine.
19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
Dreptatea ta, Dumnezeule, de asemenea este foarte înaltă, tu care ai făcut lucruri mărețe; Dumnezeule, cine este ca tine!
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
Tu, care mi-ai arătat tulburări mari și aspre, îmi vei da viață din nou și mă vei scoate din nou din adâncurile pământului.
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
Îmi vei crește măreția și mă vei mângâia din toate părțile.
22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
Eu te voi lăuda de asemenea cu psalterionul, adevărul tău, Dumnezeul meu, ție îți voi cânta cu harpa, Cel Sfânt al lui Israel.
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
Buzele mele se vor bucura mult când îți cânt; și sufletul meu, pe care tu l-ai răscumpărat.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
Limba mea de asemenea va vorbi despre dreptatea ta cât este ziua de lungă, pentru că ei sunt încurcați, pentru că sunt dați de rușine, cei ce îmi caută vătămarea.

< Psalms 71 >