< Psalms 71 >

1 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Uz tevi, Kungs, es paļaujos, ne mūžam neliec man palikt kaunā.
2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Izglāb mani caur Savu taisnību un atsvabini mani, atgriez Savu ausi pie manis un atpestī mani.
3 Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Esi man par patvērumu, kur es varu dzīvot, kur vienmēr varu bēgt. Tu esi solījis, mani atpestīt, jo Tu esi mans kalns un mana stiprā pils.
4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
Mans Dievs, izglāb mani no bezdievīgā rokas, no netaisnā un varas darītāja rokas,
5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Jo Tu esi mana cerība, Kungs, Dievs, mana drošība no manas jaunības.
6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
Uz Tevi es esmu paļāvies no mātes miesām, Tu mani esi izvilcis no mātes miesām, mana dziesma Tevi teic bez mitēšanās.
7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
Es esmu daudziem par ērmu, bet Tu esi mans stiprais patvērums.
8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
Lai mana mute pildās ar Tavu teikšanu, cauru dienu ar Tavu godu.
9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
Neatmet mani vecumā, neatstāj mani, kad spēks man zūd.
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
Jo mani ienaidnieki mani aprunā, un kas uz manu dvēseli glūn, tie kopā spriež padomu
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
Sacīdami: Dievs viņu ir atstājis, dzenaties pakaļ, sagrābiet viņu, jo glābēja nav.
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
Dievs, neesi tālu no manis, mans Dievs, steidzies man palīgā.
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Lai top kaunā, lai iet bojā, kas manai dvēselei turas pretī, ar kaunu un smieklu lai top apsegti, kas meklē manu nelaimi.
14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
Bet es vienmēr cerēšu un vairošu visu Tavu slavu.
15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
Mana mute izteiks Tavu taisnību, cauru dienu Tavu pestīšanu, jebšu to nemāku izskaitīt.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
Es staigāšu Tā Kunga spēkā, es pieminēšu Tavu taisnību, Tevi vien.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Ak Dievs, Tu mani esi mācījis no manas jaunības; un līdz šim es pasludināju Tavus brīnumus.
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
Tad nu arīdzan, kad vecums un sirmi mati ir klāt, neatstāj mani, ak Dievs, tiekams es Tavu elkoni būšu pasludinājis bērnu bērniem un Tavu stiprumu visiem pēcnākamiem.
19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
Tava taisnība, ak Dievs, ir it augsta, Tu dari lielas lietas; Dievs, kas ir tāds kā Tu?
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
Tu man lieci redzēt daudz bēdas un mokas, Tu mani darīsi atkal dzīvu, un mani izvilksi no zemes dziļumiem.
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
Vairo manu godu, un iepriecini mani atkal.
22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
Es Tevi arī slavēšu ar stīgu skaņām par Tavu uzticību, mans Dievs; es Tevi slavēšu ar koklēm, ak Svētais iekš Israēla!
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
Manas lūpas gavilēs, kad es Tev dziedāšu, un mana dvēsele, ko Tu esi atpestījis.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
Un arī mana mēle Tavu taisnību izrunās cauru dienu, jo tie ir tapuši kaunā un apkaunoti, kas meklē manu nelaimi.

< Psalms 71 >