< Psalms 71 >

1 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
J'ai cherché en toi mon refuge, ô Éternel; Que mon espoir ne soit jamais déçu!
2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Dans ta justice, délivre-moi, retire-moi du danger; Incline ton oreille vers moi, et sauve-moi!
3 Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Sois mon rocher, la retraite Où je puisse me réfugier en tout temps! Tu as donné des ordres pour que je sois sauvé; Car tu es mon rocher et ma forteresse.
4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
Mon Dieu, délivre-moi des mains du méchant, Des mains de l'homme inique et de l'oppresseur!
5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Car tu es mon espérance, ô Seigneur, Éternel! C'est en toi que je me confie depuis ma jeunesse.
6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
Je me suis appuyé sur toi dès ma naissance; C'est toi qui m'as tiré du sein de ma mère! Tu es l'objet de mes louanges en tout temps.
7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
Je suis, pour plusieurs, un sujet d'étonnement; Mais toi, tu es ma forte citadelle.
8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
Que ma bouche soit pleine de ta louange. Et qu'elle te glorifie chaque jour!»
9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
Ne me rejette pas au temps de ma vieillesse; Quand ma force s'en va, ne m'abandonne point!
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
Car mes ennemis parlent de moi; Ceux qui guettent ma vie conspirent ensemble,
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
Disant: «Dieu l'a abandonné; Poursuivez-le, saisissez-le; Car il n'y a personne pour le délivrer!»
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
Dieu! Ne t'éloigne pas de moi! Mon Dieu, accours à mon aide!
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Que ceux qui en veulent à ma vie Rougissent de honte et qu'ils périssent! Que ceux qui cherchent ma perte Soient couverts d'opprobre et de confusion!
14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
Mais moi, j'espérerai en tout temps, Et je te louerai toujours davantage.
15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
Ma bouche célébrera chaque jour Ta justice et tes délivrances. Sans jamais parvenir à énumérer tes bienfaits.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
Je raconterai partout tes grandes oeuvres, Seigneur, Éternel! C'est ta justice seule que je célébrerai.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Dieu, tu m'as instruit dès ma jeunesse. Et jusqu'à ce jour j'ai fait connaître tes oeuvres merveilleuses,
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
C'est pourquoi, jusqu'à la vieillesse. Jusqu'à la blanche vieillesse, Dieu, ne m'abandonne pas, Afin que je révèle la vigueur de ton bras à la génération nouvelle, Et ta puissance à tous ceux qui naîtront!
19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
Ta justice, ô Dieu, atteint jusqu'au ciel! Tu as accompli de grandes oeuvres. Dieu, qui est semblable à toi?
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
Après m'avoir fait passer par des détresses Et des maux sans nombre. Tu m'as de nouveau rendu la vie, Et tu m'as fait remonter des abîmes de la terre!
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
Tu accroîtras ma grandeur, Et tu me consoleras encore.
22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
Aussi, je te célébrerai sur les cordes de la lyre; Je chanterai ta fidélité, ô mon Dieu! Je psalmodierai en ton honneur sur la harpe, ô Saint d'Israël!
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
Mes lèvres, et mon âme que tu as rachetée, Entonneront des chants de joie. Quand je psalmodierai à ta gloire.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
Ma langue aussi, chaque jour, redira ta justice; Car ils seront confus, ils rougiront. Ceux qui souhaitent ma ruine!

< Psalms 71 >