< Psalms 71 >
1 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Yahweh, I have come to you to (get refuge/be protected); never allow me to become ashamed [because of being defeated].
2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Because you always do what is right, help me and rescue me; listen to me, and save me!
3 Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Be [like an overhanging] rock [MET] under which I [can be] safe/protected; [be like] a strong fortress in which I am safe [DOU]. You [continually] command (OR, [Continually] command) [your angels] to rescue me.
4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
God, rescue me from wicked [people], from the power of unjust and evil men.
5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Yahweh, my Lord, you are the one whom I confidently expect [to help me]; I have trusted in you since I was young.
6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
I have depended on you all my life; you have taken care of me [IDM] since the day that I was born, [so] I will always praise you.
7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
The manner in which I have conducted my life has been an example to many [people], because [they realize that] you have been my strong defender.
8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
I praise you all day long, and I proclaim that you are glorious/wonderful.
9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
Now, when I have become an old man, do not reject/abandon me; do not abandon me now, when I am not strong any more.
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
My enemies say [that they want to kill] me; they plan together [how they can do that].
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
They say [about me], “God has abandoned him; so now we can pursue him and seize him, because there is no one who will rescue him.”
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
God, do not stay far away from me; hurry to help me!
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Cause those who (accuse me/say that I have done things that are wrong) to be defeated and destroyed; cause those who want to harm me to be shamed and disgraced.
14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
But [as for me], I will continually and confidently expect [you to do great things for me], and I will praise you more and more.
15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
I will tell people that you do what is right; all day long I will tell people how you have saved me, although what you have done is more than I can fully understand.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
Yahweh, my Lord, I will praise you for your mighty deeds; I will proclaim that only you always act justly.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
God, you have taught me [many/those things] ever since I was young, and I still tell people about your wonderful deeds.
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
And now, God, when I am old and my hair is gray, do not abandon me. [Stay with me] while I continue to proclaim to my children and grandchildren [HYP] that you are [very] powerful!
19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
God, you do many righteous deeds; [it is as though] they extend up to the sky. You have done great things; there is no one like you [RHQ].
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
You have caused me to have many troubles and to suffer much, [but] you will cause me to become strong again; when I am almost dead [HYP], you will keep me alive.
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
You will cause me to be greatly honored and you will encourage/comfort me again.
22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
I will also praise you [while I play] my harp; I will praise you, my God, for faithfully [doing what you have promised to do]. I will play hymns to praise you, the holy God whom [we] Israelis [worship].
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
I [SYN] will shout joyfully while I play [the harp] for you; with my entire inner being I will sing because you have rescued me.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
All day long I will tell people that you act righteously, because those who wanted to harm me will have been defeated and disgraced.