< Psalms 71 >

1 Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
V tebeť, Hospodine, doufám, nechť nejsem zahanben na věky.
2 Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
Vedlé spravedlnosti své vytrhni mne, a vyprosť mne; nakloň ke mně ucha svého, a spas mne.
3 Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
Budiž mi skalou obydlí, na niž bych ustavičně utíkal; přikázal jsi ostříhati mne, nebo skála má i pevnost má ty jsi.
4 Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
Bože můj, vytrhni mne z ruky bezbožníka, z ruky převráceného a násilníka.
5 Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
Nebo ty jsi má naděje, Pane; Hospodine, v tebeť doufám od své mladosti.
6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
Na tebe jsem zpolehl hned od života, z břicha matky mé ty jsi mne vyvedl, v tobě jest chvála má vždycky.
7 Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
Jako zázrak byl jsem mnohým, a však ty jsi mé silné doufání.
8 Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
Ó ať jsou naplněna ústa má chválením tebe, přes celý den slavením tebe.
9 Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
Nezamítejž mne v věku starosti; když zhyne síla má, neopouštějž mne.
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
Nebo mluvili nepřátelé moji proti mně, a ti, jenž střehou duše mé, radili se spolu,
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
Pravíce: Bůh jej opustil, hoňte a popadněte jej, nebo kdo by ho vytrhl, není žádného.
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
Bože, nevzdalujž se ode mne, Bože můj, přispějž mi na pomoc.
13 Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Nechť jsou zahanbeni, a zhynou protivníci duše mé; přikryti buďte lehkostí a hanbou, kteříž hledají pádu mého.
14 Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
Já pak ustavičně čekati, a vždy víc a víc tě chváliti budu.
15 Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
Ústa má budou vypravovati spravedlnost tvou, každého dne spasení tvé, ačkoli mu počtu nevím.
16 Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
Přistoupě k všelijaké moci Panovníka Hospodina, připomínati budu tvou vlastní spravedlnost.
17 Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Bože, učinil jsi mne od mladosti mé, a až po dnes vypravuji o divných činech tvých.
18 Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
Protož také i do starosti a šedin, Bože, neopouštěj mne, až v známost uvedu rámě tvé tomuto věku, a všechněm potomkům sílu tvou.
19 Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
Nebo spravedlnost tvá, Bože, vyvýšená jest, provodíš zajisté věci veliké. Bože, kdo jest podobný tobě?
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
Kterýž ač jsi mi dal okusiti úzkostí velikých a hrozných, však zase k životu navrátíš mne, a z propastí země zase mne vyzdvihneš.
21 Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
Rozmnožíš důstojnost mou, a zase utěšíš mne.
22 Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
I jáť také budu tě slaviti na nástroji hudebném, i pravdu tvou, Bože můj; žalmy tobě zpívati budu na harfě, ó svatý Izraelský.
23 Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
Plésati budou rtové moji, když žalmy zpívati budu tobě, i duše má, kterouž jsi vykoupil.
24 Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.
Nadto i jazyk můj každý den vypravovati bude spravedlnost tvou; nebo se zastyděti a zahanbiti musili ti, jenž mého pádu hledali.

< Psalms 71 >