< Psalms 7 >

1 Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
Syggajon Dawida, które śpiewał PANU z powodu słów Kusza Beniaminity. PANIE, mój Boże, tobie ufam, wybaw mnie od wszystkich moich prześladowców i ocal mnie;
2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
By [ktoś] jak lew nie porwał mojej duszy i nie rozszarpał, gdy nie będzie nikogo, kto by ją ocalił.
3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
PANIE, mój Boże, jeśli to zrobiłem, jeśli nieprawość jest na moich rękach;
4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
Jeśli złem odpłaciłem temu, kto żył ze mną w pokoju, jeśli nie wyratowałem tego, który mnie dręczył bez przyczyny;
5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
To niech wróg prześladuje moją duszę i niech pochwyci i wdepcze w ziemię moje życie, niech moją godność w proch obróci. (Sela)
6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Powstań, PANIE, w swoim gniewie; podnieś się przeciwko wściekłości moich wrogów. Przebudź się w mojej obronie, bo ustanowiłeś sąd.
7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
Wtedy otoczy cię zgromadzenie narodów, a ty zasiądź na wysokości ze względu na nich.
8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
PAN będzie sądził narody. Osądź mnie, PANIE, według mojej sprawiedliwości i według mojej uczciwości, która jest we mnie.
9 Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
Niech skończy się zło niegodziwych, a umocnij sprawiedliwego, Boże sprawiedliwy, ty, który badasz serca i nerki.
10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
Moją tarczą jest Bóg, który wybawia [ludzi] prawego serca.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
Bóg jest sędzią sprawiedliwym, Bóg codziennie gniewa się [na bezbożnego].
12 Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
Jeśli się nie nawróci, on swój miecz naostrzy; swój łuk napiął i przygotował go.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
Przygotował na niego broń śmiertelną, a swoje strzały sporządził na prześladowców.
14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
Oto [bezbożny] rodzi nieprawość, jest brzemienny krzywdą i zrodził kłamstwo.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
Wykopał dół i pogłębił go, lecz sam wpadnie do jamy, którą przygotował.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
Krzywda, którą wyrządzał, obróci się przeciwko niemu, a jego nieprawość spadnie mu na głowę.
17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.
Będę wysławiał PANA według jego sprawiedliwości, będę śpiewał imieniu PANA Najwyższego.

< Psalms 7 >