< Psalms 7 >

1 Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
Ratapan Daud, yang dinyanyikan bagi TUHAN karena Kus, orang Benyamin itu. Ya TUHAN Allahku, aku berlindung pada-Mu; selamatkanlah dan lepaskanlah aku dari semua orang yang mengejar aku.
2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
Jangan biarkan mereka seperti singa menerkam dan menyeret aku dan tak ada pertolongan bagiku.
3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
Ya TUHAN Allahku, sekiranya aku berlaku curang, berbuat jahat terhadap kawan, atau merugikan lawan tanpa alasan, sekiranya aku berbuat demikian,
4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
biarlah aku dikejar dan ditangkap musuh, lalu dibunuh dan ditinggalkan di tanah.
6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Bangkitlah dalam kemarahan-Mu, ya TUHAN, lawanlah amukan musuh-musuhku. Bangkitlah untuk menolong aku, sebab Engkau menuntut keadilan.
7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
Himpunlah bangsa-bangsa di sekeliling-Mu, dan berkuasalah atas mereka dari takhta-Mu di surga.
8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
Engkau menghakimi umat manusia; berilah aku keadilan, ya TUHAN, sebab aku tidak bersalah.
9 Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
Hentikanlah kejahatan orang durhaka dan teguhkanlah hati orang baik, sebab Engkau Allah yang adil, yang menyelami hati dan pikiran manusia.
10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
Pelindungku ialah Allah yang menyelamatkan orang yang tulus hati.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
Allah adalah hakim yang adil, yang setiap saat menghukum orang jahat.
12 Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
Kalau kelakuan mereka tidak berubah, Ia siap dengan senjata yang mematikan. Ia mengasah pedangnya dan merentangkan busurnya, lalu membidikkan panah-panah-Nya yang berapi.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
Lihatlah, orang jahat merencanakan kejahatan; ia membuat rencana jahat dan melakukan penipuan.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
Ia menggali lubang untuk orang lain, tetapi ia sendiri jatuh ke dalamnya.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
Jadi ia dihukum oleh kejahatannya sendiri, dan disiksa oleh kekerasannya sendiri.
17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.
Aku bersyukur kepada TUHAN sebab Ia adil, kunyanyikan pujian bagi TUHAN, Yang Mahatinggi.

< Psalms 7 >