< Psalms 7 >

1 Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
Siggájón Dávidtól, melyet énekelt az Örökkévalónak a Benjáminbeli Kús dolgában. Örökkévaló, Istenem, benned keresek menedéket; segíts engem mind az üldözőimtől, és ments meg engem!
2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
Nehogy oroszlánként széttépje lelkemet, ragadozva s nincs, a ki megment.
3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
Örökkévaló, Istenem, ha én tettem ezt, ha van jogtalanság kezeimen,
4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
ha rosszat követtem el a velem békében levővel, – hisz kiszabadítottam azt, ki ok nélkül szorongatott -:
5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
üldözze ellenség lelkemet, s érje utól és tiporja földre éltemet, és fektesse porba méltóságomat! Széla.
6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Kelj föl, Örökkévaló, haragodban, emelkedjél szorongatóim dühöngései ellen; és serkenj értem: ítéletet rendeltél.
7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
Nemzetek gyülekezete körülvesz téged és fölötte térj vissza a magasságba!
8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
Az Örökkévaló népeket itél, szerezz jogot nekem, Örökkévaló, igazságom szerint és gáncstalanságom szerint, mely bennem van.
9 Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
Szűnjék meg, kérlek, a gonoszok rosszasága és szilárdítsd meg az igazat! Hiszen szívek és vesék vizsgálója az igazságos Isten!
10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
Paizsom Istennél van, ki segíti az egyenesszívűeket.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
Isten igazságos bíró, Isten ő, ki mindennap haragszik.
12 Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
Ha ki meg nem tér, kardját feni, íjját feszítotte és irányította;
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
és ellene elkészított halálos fegyvereket, nyílait égőkké csinálja.
14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
Íme vajudik jogtalansággal; bajt fogant és hazugságot szűlt.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
Vermet ásott és kivájta azt, de beleesett a gödörbe, melyet csinált.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
Visszahárul baja a maga fejére, és az ő feje tetejére száll le erőszaka.
17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.
Hadd magasztalom az Örökkévalót igazsága szerint, hadd zengem nevét az Örökkévalónak, a legfelsőnek!

< Psalms 7 >