< Psalms 7 >
1 Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
A Shiggaion of David which he sang to Yahweh on [the] words of Cush a Ben-jaminite. O Yahweh God my in you I have sought refuge save me from all pursuers my and deliver me.
2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
Lest he should tear to pieces like a lion self my tearing and there not [is] a deliverer.
3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
O Yahweh God my if I have done this if there [is] unrighteousness in hands my.
4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
If I have repaid [one who] is at peace with me evil and I have rescued! opposer my without cause.
5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
May he pursue an enemy - life my and may he overtake [it] and he may trample to the earth life my and honor my - to the dust may he lay (Selah)
6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Arise! O Yahweh - in anger your raise yourself on [the] furi of opposers my and awake! to me justice you have commanded.
7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
And an assembly of nations may it surround you and over it to the height return!
8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
Yahweh let him judge peoples vindicate me O Yahweh according to righteousness my and according to integrity my on me.
9 Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
May it come to an end please [the] evil of - wicked [people] and may you establish [the] righteous and [who] tests hearts and kidneys O God righteous.
10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
Shield my [is] on God a deliverer of [people] upright of heart.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
God [is] a judge righteous and God [is] indignant on every day.
12 Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
If not anyone will repent sword his he will sharpen bow his he has bent and he has prepared it.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
And for him he has prepared weapons of death arrows his into burning [things] he will make.
14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
There! he is in labor with wickedness and he conceives mischief and he brings forth falsehood.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
A pit he digs and he has dug it and he has fallen in [the] pit [which] he made.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
It returns mischief his on own head his and on scalp his violence his it comes down.
17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.
I will give thanks to Yahweh according to righteousness his and I will sing praise to [the] name of Yahweh [the] Most High.