< Psalms 7 >

1 Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
O LORD my God, in you do I put my trust: save me from all them that persecute me, and deliver me:
2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
Lest he tear my soul like a lion, rending it in pieces, while there is none to deliver.
3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
O LORD my God, If I have done this; if there be iniquity in my hands;
4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
If I have rewarded evil unto him that was at peace with me; (yea, I have delivered him that without cause is mine enemy: )
5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
Let the enemy persecute my soul, and take it; yea, let him tread down my life upon the earth, and lay mine honour in the dust. (Selah)
6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Arise, O LORD, in your anger, lift up yourself because of the rage of mine enemies: and awake for me to the judgment that you have commanded.
7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
So shall the congregation of the people compass you about: for their sakes therefore return you on high.
8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
The LORD shall judge the people: judge me, O LORD, according to my righteousness, and according to mine integrity that is in me.
9 Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
Oh let the wickedness of the wicked come to an end; but establish the just: for the righteous God tries the hearts and reins.
10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
My defence is of God, which saves the upright in heart.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
God judges the righteous, and God is angry with the wicked every day.
12 Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
If he turn not, he will sharpen his sword; he has bent his bow, and made it ready.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
He has also prepared for him the instruments of death; he ordains his arrows against the persecutors.
14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
Behold, he labors with iniquity, and has conceived mischief, and brought forth falsehood.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
He made a pit, and dug it, and is fallen into the ditch which he made.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
His mischief shall return upon his own head, and his violent dealing shall come down upon his own crown of the head.
17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.
I will praise the LORD according to his righteousness: and will sing praise to the name of the LORD most high.

< Psalms 7 >