< Psalms 69 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
Neghmichilerning béshigha tapshurulup, «Niluperler» dégen ahangda oqulsun dep, Dawut yazghan küy: — Méni qutquzghaysen, i Xuda! Sular jénimdin ötti;
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Turghudek jay yoq chongqur patqaqliqqa chöküp kettim; Suning chongqur yérige chüshüp kettim, Kelkün méni gherq qildi.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Peryadlirimdin halimdin kettim; Gallirim qurup ketti; Xudayimgha telmürüp, közümdin kétey dep qaldim;
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Sewebsiz manga öch bolghanlar chachlirimdinmu köptur; Méni yoqatmaqchi bolghanlar, Qara chaplap men bilen düshmenlishidighanlar küchlüktur; Shu chaghda özüm bulimighan nersini qayturimen.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
I Xuda, méning nadanliqim özüngge ayan; Méning qebihliklirim Sendin yoshurun emestur.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Méning sewebimdin, i Reb, samawiy qoshunlarning Serdari bolghan Perwerdigar, Özüngge umid baghlap kütkenler yerge qarap qalmighay; I Israilning Xudasi, Özüngni izdigüchiler méning sewebimdin shermende bolmighay;
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Chünki Séni dep men reswachiliqqa uchridim; Shermendilik yüzümge chaplandi.
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
Men öz qérindashlirimgha yat, Anamning balilirigha yaqa yurtluq boldum.
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
Chünki méni [muqeddes] öyüngge bolghan otluq muhebbet chulghuwalghanidi; Sanga haqaret qilghanlarning haqaretlirimu méning üstümge chüshti;
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Men yighlidim, jénim roza tutti, Bumu manga eyib dep qaraldi.
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
Men bözni kiyimim qilip kiysem, Shuning bilen ularning söz-chöchikige qaldim.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
Sheher qowuqida olturghanlarning tene gépige qaldim, Meyxorlarning naxshisining témisi boldum.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
Biraq men shepqitingni körsetken waqtingda duayimni sanga nishanlidim, i Perwerdigar; I Xuda, özgermes muhebbitingning zorluqidin, Nijatliq ishenchide manga jawab bergeysen;
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Méni patqaqliqtin qutquzuwalghaysen, Méni chöktürmigeysen; Manga öchmen bolghanlardin, Suning chongqur yéridin qutuldurghaysen;
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Kelkün sulirigha méni gherq qildurmighaysen; Déngiz teglirigimu méni yutquzmighaysen; [Tégi] yoq hangning méni hap étip aghzini yumuwélishigha yol qoymighaysen!
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Duayimni ijabet qilghaysen, i Perwerdigar, Chünki özgermes muhebbiting yaxshidur; Mol rehimdilliqing bilen manga yüzlen’geysen;
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
Jamilingni qulungdin yoshurmighaysen; Chünki béshimgha kün chüshti; Tézdin manga jawab bergeysen.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Jénimgha yéqinlashqaysen, Uninggha hemjemet-qutquzghuchi bolghaysen; Düshmenlirim aldida méni hörlükke chiqarghaysen;
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
Özüng méning reswaliqta hem hörmetsizlikte qalghinimni, Qandaq haqaretlen’ginimni bilisen; Reqiblirimning hemmisi Özüngge ayandur.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Haqaret qelbimni pare qildi; Men qayghugha chömüp kettim; Azghine hésdashliqqa telmürgen bolsammu, yoq boldi; Teselli bergüchilernimu izdidim, lékin birsinimu uchritalmidim.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
Berheq, ular ozuqumgha öt süyi, Ussuzluqumgha sirkini berdi.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Ularning dastixini özlirige qiltaq, Ularning halawiti qapqan bolghay.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Közliri torliship körmeydighan bolup ketkey; Bel-putlirini titrekke salghaysen;
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Qehringni ularning üstige chüshürgeysen, Ghezipingning otliri ulargha tutashqay;
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Ularning makani xarabe bolghay, Chédirliri chölderep qalghay;
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Chünki ular Sen urghan’gha téximu ziyankeshlik qilmaqta; Sen zeximlendürgenlerning azabigha gep bilen azab qoshmaqta.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Ularning gunahigha gunah qoshqaysen, Heqqaniyliqingning nésiwisige ularni érishtürmigeysen.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Ular hayatliq deptiridin öchürülgey; Heqqaniylarning qatarigha pütülmigey.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
Biraq men bolsam bir ézilgen derdmen; Nijatliqing, i Xuda, méni yuqirigha kötürüp qutquzghay;
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
Men munajat oqup Xudaning namini medhiyileymen; Teshekkürler bilen uni ulughlaymen;
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
Bu bolsa Perwerdigarni xursen qilish üchün, Öküz teqdim qilghandin ewzeldur; Münggüz-tuyaqliri saq torpaq bergendinmu artuqtur.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
Yawash möminler buni körüp xushal bolidu; Xudani izdigenler — Qelbinglar yéngilinidu.
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Chünki Perwerdigar yoqsullarning iltijasini anglaydu, Özige tewe esir qilin’ghanlarni u kemsitmeydu;
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Asman-zémin Uni medhiyilisun! Déngiz-okyanlar hem ularda yürgüchi barliq janiwarlar Uni medhiyiligey!
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
Chünki Xuda Zionni qutquzidu; Yehudaning sheherlirini qayta bina qilidu; Ular ashu yerde olturaqliship, igilik tikleydu.
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Uning qullirining nesilliri uninggha miras bolidu, Uning namini söygenler u yerlerde makanlishidu.

< Psalms 69 >