< Psalms 69 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
Reši me, oh Bog, kajti vode vstopajo v mojo dušo.
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Tonem v globoko blato, kjer ni stojišča. Prišel sem v globoke vode, kjer me preplavljajo poplave.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Naveličan sem svojega joka, moje grlo je suho, moje oči pešajo, ko čakam na svojega Boga.
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Tistih, ki me sovražijo brez razloga, je več kakor las moje glave. Tisti, ki me hočejo uničiti, so moji krivični sovražniki, mogočni so. Potem sem povrnil to, česar nisem vzel.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
Oh Bog, ti poznaš mojo nespametnost in moji grehi niso skriti pred teboj.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Naj tisti, ki čakajo nate, oh Gospod Bog nad bojevniki, ne bodo osramočeni zaradi mene. Naj tisti, ki te iščejo, ne bodo zbegani zaradi mene, oh Izraelov Bog.
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Ker zaradi tebe prenašam grajo, je moj obraz pokrila sramota.
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
Postal sem tujec svojim bratom in neznanec otrokom svoje matere.
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
Kajti gorečnost za tvojo hišo me je použila in graje teh, ki so te grajali, so padle name.
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Ko sem jokal in svojo dušo karal s postom, je bilo to za mojo grajo.
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
Tudi vrečevino sem si naredil za svojo obleko in postal sem jim v pregovor.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
Tisti, ki sedijo v velikih vratih, govorijo zoper mene in bil sem pesem pijancem.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
Toda, kar se mene tiče, je moja molitev k tebi, oh Gospod, ob sprejemljivem času. Oh Bog, v množici svojih usmiljenj me usliši, v resnici tvoje rešitve duše.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Osvobodi me iz blata in ne pusti me utoniti. Naj bom osvobojen pred temi, ki me sovražijo in ven iz velikih vodá.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Naj me ne preplavi voda niti naj me ne požre globina in jama naj ne zapre svojih ust nad menoj.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Usliši me, oh Gospod, kajti tvoja ljubeča skrbnost je dobra. Obrni se k meni glede na množino svojih nežnih usmiljenj.
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
Svojega obraza ne skrij pred svojim služabnikom, kajti v stiski sem. Naglo me usliši.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Približaj se moji duši in odkupi jo. Osvobodi me zaradi mojih sovražnikov.
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
Spoznal si mojo grajo in mojo sramoto ter mojo nečast. Moji nasprotniki so vsi pred teboj.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Graja je zlomila moje srce in poln sem potrtosti. Pričakoval sem kakega, da se usmili, toda ni bilo nobenega; in tolažnikov, toda nisem našel nobenega.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
Za jed so mi dali tudi žolč in v moji žeji so mi dali piti kis.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Njihova miza naj pred njimi postane zanka, in to, kar naj bi bilo za njihovo blaginjo, naj postane past.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Naj njihove oči otemnijo, da ne vidijo in njihovim ledjem stôri, da se nenehno tresejo.
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Nanje izlij svoje ogorčenje in naj jih zgrabi tvoja srdita jeza.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Naj bo njihovo prebivališče zapuščeno in naj nihče ne prebiva v njihovih šotorih.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Kajti preganjajo tistega, ki si ga ti udaril in govorijo v žalost tistih, ki si jih ranil.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Njihovi krivičnosti dodaj krivičnost, in naj ne pridejo v tvojo pravičnost.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Naj bodo izbrisani iz knjige življenja in ne bodo zapisani s pravičnimi.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
Toda jaz sem ubog in žalosten. Naj me tvoja rešitev duše, oh Bog, postavi visoko gor.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
S pesmijo bom hvalil Božje ime in ga poveličeval z zahvaljevanjem.
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
To bo tudi bolj ugajalo Gospodu kakor vol ali bikec, ki ima roge in kopita.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
Ponižni bo to videl in bil vesel in vaše srce, ki išče Boga, bo živelo.
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Kajti Gospod posluša uboge in ne prezira svojih jetnikov.
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Naj ga hvalita nebo in zemlja, morja in vsaka stvar, ki se giblje v njih.
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
Kajti Bog bo rešil Sion in pozidal Judova mesta, da bodo lahko tam prebivali in to imeli v posesti.
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Tudi seme njegovih služabnikov bo to podedovalo in tisti, ki ljubijo njegovo ime, bodo prebivali v njih.

< Psalms 69 >