< Psalms 69 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
Przedniejszemu śpiewakowi na Sosannim psalm Dawidowy. Wybaw mię, o Boże! boć przyszły wody aż do duszy mojej.
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Pogrążony jestem w głębokiem błocie, gdzie dna niemasz; przyszedłem w głębokości wód, a nawałność ich porwała mię.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Spracowałem się wołając, wyschło gardło moje; ustały oczy moje, gdym oczekiwał Boga mojego.
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Więcej jest tych, którzy mię mają w nienawiści bez przyczyny, niż włosów na głowie mojej; zmocnili się ci, którzy mię wygubić usiłują, a są nieprzyjaciółmi mymi niesłusznie; czegom nie wydarł, musiałem nagradzać.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
Boże! ty znasz głupstwo moje, a występki moje nie są tajne przed tobą.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Niechajże nie będą zawstydzeni dla mnie ci, którzy na cię oczekują, Panie, Panie zastępów! niech nie przychodzą dla mnie do hańby ci, którzy cię szukają, o Boże Izraelski!
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Bo dla ciebie ponoszę urąganie, a zelżywość okryła oblicze moje.
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
Stałem się obcym braciom moim, a cudzoziemcem synom matki mojej,
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
Przeto, że gorliwość domu twego zżarła mię, a urąganie urągających tobie przypadło na mię.
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Gdym płakał i trapił postem duszę moję, stało mi się to pohańbienie.
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
Gdym wziął na się wór miasto szaty, byłem u nich przypowieścią.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
Mówili o mnie ci, którzy siedzieli w bramie, a byłem piosnką u tych, którzy pili mocny napój.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
Ale ja obracam modlitwę moję do ciebie, Panie! czas jest upodobania twego; o Boże! według wielkości miłosierdzia twego wysłuchajże mię, dla prawdy zbawienia twego.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Wyrwij mię z błota, abym nie był pogrążony; niech będę wyrwany od tych, którzy mię nienawidzą, jako z głębokości wód;
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Aby mię nie zatopiły strumienie wód, i nie pożarła głębia i nie zawarła nademną studnia wierzchu swego.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Wysłuchajże mię, Panie! boć dobre jest miłosierdzie twoje; według wielkiej litości twojej wejrzyj na mię.
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
Nie zakrywajże oblicza twego od sługi swego, bom jest w utrapieniu; pośpieszże się, wysłuchaj mię.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Przybliż się do duszy mojej, a wybaw ją; dla nieprzyjaciół moich odkup mię.
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
Ty znasz pohańbienie moje, i zelżywość moję, i wstyd mój: przed tobąć są wszyscy nieprzyjaciele moi.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Pohańbienie pokruszyło serce moje, z czegom był żałośny; oczekiwałem, azaliby się mię kto użalił, ale nikt nie był; azaliby mię kto pocieszył, alem nie znalazł.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
Owszem, miasto pokarmu podali mi żółć, a w pragnieniu mojem napoili mię octem.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Niechajże im będzie stół ich przed nimi sidłem, a szczęście ich na upadek.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Niech się zaćmią oczy ich, aby nie widzieli, a biodra ich niech się zawżdy chwieją.
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Wylij na nich rozgniewanie swoje, a popędliwość gniewu twego niech ich ogarnie.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Niech będzie mieszkanie ich puste, w namiotach ich niech nikt nie mieszka.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Bo tego, któregoś ty ubił, prześladują, a o boleści poranionych twoich rozmawiają.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Przydajże nieprawość ku nieprawości ich, a niech nie przychodzą do sprawiedliwości twojej.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Niech będą wymazani z ksiąg żyjących, a z sprawiedliwymi niech nie będą zapisani.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
Jamci utrapiony, i zbolały; lecz zbawienie twoje, Boże! na miejscu bezpiecznem postawi mię.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
Tedy będę chwalił imię Boże pieśnią, a będę je wielbił z dziękczynieniem.
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
A będzie to przyjemniejsze Panu, niżeli wół albo cielec rogaty z rozdzielonemi kopytami.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
To widząc pokorni rozradują się, szukając Boga, a ożyje serce ich;
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Iż wysłuchiwa Pan ubogich, a więźniami swymi nie gardzi.
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Niech go chwalą niebiosa i ziemia, morze i wszystko, co się w nich rucha.
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
Bógci zaiste zachowa Syon, i pobuduje miasta Judzkie; i będą tam mieszkać, a ziemię tę dziedzicznie otrzymają.
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Także i nasienie sług jego dziedzicznie ją otrzyma, a którzy miłują imię jego, będą w niej mieszkać.

< Psalms 69 >