< Psalms 69 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
A karmesternek. Liliomok szerint. Dávidtól. Segíts engem Isten, mert lélekig hatoltak a vizek.
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Belesülyedtem a mélység iszapjába, s nincs megállhatás; bejutottam vizek mélyeibe és áradat sodort el engem.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Elfáradtam kiáltásomban, kihevült a torkom, elepedtek szemeim, várván Istenemre.
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Többen vannak fejem haj szálainál, kik ok nélkül gyülölöim, számosak a megsemmisítőim, kik hazugul ellenségeim; a mit el nem raboltam, azt kell megtérítenem.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
Isten, te ismered oktalanságomat, és bűneim előtted nincsenek eltitkolva.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Ne szégyenűljenek meg általam a téged remélők, Uram, Örökkévaló, seregek ura; ne piruljanak el általam a téged keresők, Izraél Istene.
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Mert éretted viseltem gyalázatot, boritotta szégyen arczomat;
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
elidegenítve lettem testvéreimnek, isméretlenné anyám fiainak.
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
Mert a házadért való buzgólkodás megemésztett engem, és gyalázóid gyalázásai én reám estek.
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Bőjtben sírtam lelkemből, gyalázássá lett nekem;
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
öltözetemmé zsákot tettem: lettem nekik példabeszéddé.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
Szólnak rólam a kapuban ülők és a borivóknak danái.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
De én – hozzád van az imádságom, Örökkévaló, a kegy idején; Isten, nagy szeretetedben hallgass meg engem üdvöd igazságával.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Ments ki engem a sárból, s ne engedj elsülyednem; hadd menekülök meg gyűlölőimtől s vizek mélyeiből.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Ne sodorjon el a viz áradata s ne nyeljen el a mélység, s ne zárja rám száját a verem.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Hallgass meg, Örökkévaló, mert jó a szereteted, nagy irgalmad szerint fordulj hozzám.
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
S ne rejtsd el arczodat szolgádtól; mert megszorultam, gyorsan hallgass meg.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Közeledj lelkemhez, váltsd meg azt, ellenségeim okából válts ki engem.
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
Te ismered gyalázatomat, szégyenemet és pirulásomat; előtted vannak mind a szorongatóim.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Gyalázat törte meg szívemet és sínylődtem; reméltem megszánást, de nincs, vigasztalókat, de nem találtam.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
Étkemül adtak mérget és szomjamra itattak velem eczetet.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Legyen asztaluk előttük tőrré és a bátorságosaknak csapdává.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Sötétűljenek el szemeik, hogy ne lássanak, és derekukat mindig tántorogtasd meg.
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Öntsd ki rájuk haragvásodat, és föllobbant haragod érje utól őket.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Legyen tanyájuk elpusztult, sátraikban ne legyen lakó.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Mert a kiket te megvertél, üldözték, és megöltjeid fájdalmáról beszélnek.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Tégy bűnt a bűnükre s ne jussanak be igazságodba.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Törültessenek ki az élők könyvéből és igazakkal együtt be ne irassanak.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
Én pedig szegény és szenvedő vagyok; segítséged, oh Isten, ótalmazzon engem.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
Hadd dicsérem Isten nevét énekkel és nagynak mondom őt hálaszóval,
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
az jobban tetszik az Örökkévalónak ökörnél, szarvas-patás tuloknál.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
Látták az alázatosak, örülnek; Istent keresők ti, éledjen föl szívetek!
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Mert hallgat a szűkölködőkre az Örökkévaló, s az ő foglyait nem vetette meg.
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Dicsérjék őt ég és föld, tengerek s mind a mi mozog bennök:
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
mert Isten megsegíti Cziónt s fölépíti Jehúda városait, hogy lakjanak ott. és birtokba vegyél;
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
és szolgáinak magzata örökli azt, a kik nevét szeretik, lakoznak benne.