< Psalms 69 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
Thaburi ya Daudi Wee Ngai-rĩ, honokia, nĩgũkorwo maaĩ maanginyĩte o ngingo.
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Ndĩratoonyerera mũtondo-inĩ mũriku, handũ hatarĩ na ha gũkinyithia kũgũrũ. Nginyĩte maaĩ-inĩ harĩa hariku; mũiyũro wa maaĩ nĩũhumbĩkanĩtie.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Nĩnogete mũno nĩ gũkaya ndeithio; mũmero wakwa nĩ mũngʼaru. Maitho makwa nĩmorĩtwo nĩ hinya nĩgũcũthĩrĩria Ngai wakwa.
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Andũ arĩa maathũire hatarĩ gĩtũmi nĩ aingĩ gũkĩra njuĩrĩ cia mũtwe wakwa; thũ ciakwa iria iithũire hatarĩ gĩtũmi nĩ nyingĩ, o icio injaragia iniine. Hatagĩrĩrio njookie kĩndũ itaiyĩte.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
Wee Ngai nĩũũĩ ũrimũ wakwa; mahĩtia makwa matingĩhithĩka harĩwe.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Andũ arĩa makwĩhokete, maroaga gũconorithio nĩ ũndũ wakwa, Wee Mwathani, Jehova Mwene-Hinya-wothe; arĩa makũrongoragia maroaga kũnyararwo nĩ ũndũ wakwa, Wee Ngai wa Isiraeli.
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Nĩgũkorwo nĩngirĩrĩirie kũmenwo nĩ ũndũ waku, naguo ũthiũ wakwa nĩũhumbĩtwo thoni.
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
Nduĩkĩte ta mũgeni harĩ ariũ a baba, ngatuĩka ta mũndũ wa kũngĩ harĩ ariũ a maitũ;
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
kĩyo kĩrĩa ndĩ nakĩo kĩa nyũmba yaku nĩkĩo kĩrandĩa, irumi cia arĩa makũrumaga nĩ niĩ igũĩrĩire.
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Rĩrĩa ngũrĩra na ngehinga kũrĩa irio, no nginya ngirĩrĩrie kũnyũrũrio;
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
rĩrĩa ndehumba nguo ya ikũnia, andũ no gũũthekerera.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
Andũ arĩa maikaraga kĩhingo-inĩ gĩa itũũra nĩ niĩ manyũrũragia, na nduĩkĩte rwĩmbo rwa arĩĩu.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
Wee Jehova, nĩndakũhooya hĩndĩ ĩrĩa ya gwĩtĩkĩrĩka nĩwe; Wee Ngai, nĩ ũndũ wa wendo waku mũnene, ũnjĩtĩke na ũhonokio waku wa ma.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Honokia ũndute mũtondo-inĩ, ndũkareke ndoonyerere; ndeithũra kuuma kũrĩ arĩa maathũire, ũndute kuuma maaĩ-inĩ marĩa mariku.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Ndũkareke mũiyũro wa maaĩ ũũhubĩkanie, kana merio nĩ kũrĩa kũriku, o na kana ndumĩrio kanua nĩ irima rĩa gĩkuũ.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Wee Jehova, njĩtĩka nĩ ũndũ wa wega wa wendo waku; nĩ ũndũ wa tha ciaku nyingĩ wĩhũgũre ũnjookerere.
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
Ndũkahithe ndungata yaku ũthiũ waku; njĩtĩka narua, nĩgũkorwo ndĩ thĩĩna-inĩ.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Ũka hakuhĩ ũndeithũre; honokia kuuma kũrĩ thũ ciakwa.
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
We nĩũũĩ ũrĩa nyũrũrĩtio, na ngaconorithio na ngahumbwo thoni; thũ ciakwa ciothe irĩ mbere yaku.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Kũnyũrũrio nĩ gũũthuthĩte ngoro ngatigwo itarĩ na mwĩhoko; ndeetereire nyone wa kũnjiguĩra tha, no ndiigana kũmuona, ngĩeterera nyone andũ a kũũhooreria, no ndiamonire.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
Maanjĩkĩrĩire maaĩ ma nyongo irio-inĩ ciakwa, na ndanyoota makĩĩhe thiki nyue.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Metha ĩrĩa maarĩirwo ĩrotuĩka mũtego; ĩrotuĩka ihũũra o na mũtego wa kũmagwatia.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Maitho mao marogĩa nduma matige gũcooka kuona, nayo mĩgongo yao ĩrohocerera nginya tene.
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Maitũrũrĩre mangʼũrĩ maku; makinyĩrie marakara maku mahiũ.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Mĩciĩ yao ĩrokira ihooru; kũroaga mũndũ wa gũtũũra hema-inĩ ciao.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Nĩgũkorwo manyariiraga arĩa wee ũgurarĩtie, na makaaria ũhoro wa ruo rwa arĩa ũtiihĩtie.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Mathitangĩre o ngero thuutha wa ĩrĩa ĩngĩ; ndũkanareke magatoonya ũhonokanio-inĩ waku.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Marothario ibuku-inĩ rĩa muoyo, mage kwandĩkwo mũtaratara-inĩ wa andũ arĩa athingu.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
Ndĩ na ruo na ngathĩĩnĩka; Wee Ngai kĩĩhonokie na ũngitĩre.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
Nĩngũgooca rĩĩtwa rĩa Ngai na rwĩmbo, na ndĩmũtũũgĩrie ngĩmũcookagĩria ngaatho.
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
Naguo ũndũ ũcio nĩũgũgĩkenia Jehova gũkĩra kũmũhe ndegwa, na gũkĩra ndegwa nene ĩrĩ na hĩa na mahũngũ.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
Andũ arĩa athĩĩni mona ũguo nĩmagakena; inyuĩ arĩa mũrongoragia Ngai, ngoro cianyu iroarahũka!
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Jehova nĩathikagĩrĩria arĩa abatari, na ndangĩnyarara andũ ake moohetwo.
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Igũrũ na thĩ nĩimũgooce, o na maria marĩa manene na kĩrĩa gĩothe gĩthiiagĩra thĩinĩ wamo,
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
nĩgũkorwo Ngai nĩakahonokia Zayuni, na aake matũũra marĩa manene ma Juda rĩngĩ. Hĩndĩ ĩyo andũ nĩmagatũũra kuo na makwĩgwatĩre;
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
ciana cia ndungata ciake nĩigakũgaya, nao arĩa mendete rĩĩtwa rĩake nĩmagatũũra kuo.

< Psalms 69 >