< Psalms 69 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
За първия певец, по криновете, Давидов псалом Избави ме, Боже; Защото водите стигнаха до душата ми.
2 Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
Потъвам в дълбока тиня, гдето няма твърдо място да застана; Стигнах в дълбоки води, гдето потопът ме покрива.
3 Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
Изнемогвам от викане; гърлото ми е изсъхнало; Очите ми чезнат, докато чакам моя Бог.
4 Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
Тия, които ме мразят без причина, се умножиха повече от космите на главата ми; Укрепиха се моите погубители, които неправедно са мои неприятели; Тогава ме заставиха да върна онова, което не бях грабнал.
5 Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
Боже, Ти знаеш безумието ми; И прегрешенията ми не са скрити от Тебе.
6 Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
Господи Иеова на Силите, да се не посрамят покрай мене ония, които Те чакат; Боже Израилев, да се на опозорят покрай мене ония, които Те търсят.
7 Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
Защото заради Тебе претърпях поругание. Срам покри лицето ми.
8 Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
Чужда станах на братята си, И странен на чадата на майка ми.
9 nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
Защото ревността за Твоя дом ме изяде, И укорите на ония, които укоряват Тебе, паднаха върху мене.
10 Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
Когато плачех в душата си с пост, Това ми стана за укор;
11 nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
Когато облякох вретище за дреха, Станах им за поговорка.
12 Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
За мене приказват седящите в портата; И аз станах песен на пияниците.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
Но аз към Тебе отправям молитвата си, Господи, в благоприятно време; Боже, послушай ме според голямата Твоя милост, Според верността на Твоето спасение.
14 Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
Избави ме от тинята, за да не потъна; Нека бъда избавен от ония, които ме мразят, и от дълбоките води.
15 Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
Не дай да ме завлече устрема на водите, Нито да ме погълне дълбочината; И не дай да затвори ямата устието си над мене.
16 Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
Послушай ме, Господи, защото е благо Твоето милосърдие; Според много Твои благи милости погледни на мене;
17 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
И не скривай лицето Си от слугата Си, Понеже съм в утеснение; бърже ме послушай.
18 Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Приближи се при душата ми и я изкупи; Изкупи ме поради неприятелите ми.
19 Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
Ти знаеш как ме укоряват, Как ме посрамват и ме опозоряват; Пред тебе са всичките мои противници.
20 Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
Укор съкруши сърцето ми, и съм много отпаднал; И чаках да ме пожали някой, но нямаше никой, - И утешители, но не намерих.
21 Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
И дадоха ми жлъчка за ядене, И в жаждата ми ме напоиха с оцет.
22 Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
Трапезата им пред тях нека им стане примка, И когато са на мира нека стане клопка.
23 Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
Да се помрачат очите им та да не видят; И чреслата им направи непрестанно да се тресат.
24 Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Излей на тях негодуванието Си; И пламъкът на гнева Ти нека ги постигне.
25 Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
Жилището им да запустее, И в шатрите им да няма кой да живее.
26 Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
Защото те гонят онзи, когото Ти си поразил, И говорят за болката на ония, които Ти си наранил.
27 Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
Приложи беззаконие на беззаконието им; И да не участвуват в Твоята правда.
28 Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
Да се изличат от книгата на живота, И с праведните да се не запишат.
29 Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
А мене, който съм сиромах и скръбен, Да ме възвиши, Боже, Твоето спасение.
30 Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
Ще хваля името на Бога с песен, И ще Го възвелича с хваления;
31 Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
И това ще угоди Господу Повече от вол, - от юнец имащ рога и копита.
32 Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
Смирените ще видят и ще се зарадват; И вие, които търсите Бога, вашето сърце ще се съживи.
33 Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
Защото Господ слуша немощните, И запрените Си не презира.
34 Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
Нека Го хвалят небето и земята, Моретата, и всичко, което се движи в тях.
35 nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
Защото Бог ще избави Сиона, и ще съгради Юдовите градове; И людете Му ще се заселят там, и ще го владеят.
36 àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.
Още и потомството на слугите Му ще го наследи, И ония, които обичат името Му, ще живеят в него.

< Psalms 69 >