< Psalms 68 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
Müzik şefi için - Davut'un mezmuru - İlahi Kalksın Tanrı, dağılsın düşmanları, Kaçsın önünden O'ndan nefret edenler!
2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Dağıtsın onları dağılan duman gibi; Ateşin karşısında eriyen balmumu gibi Yok olsun kötüler Tanrı'nın önünde!
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
Ancak doğrular sevinsin, Bayram etsinler Tanrı'nın önünde, Neşeyle coşsunlar.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
Tanrı'ya ezgiler söyleyin, adını ilahilerle övün, Çölleri geçecek biniciye yol hazırlayın; O'nun adı RAB'dir, bayram edin önünde!
5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
Kutsal konutundaki Tanrı, Öksüzlerin babası, dul kadınların savunucusudur.
6 Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
Tanrı kimsesizlere ev verir, Tutsakları özgürlüğe ve gönence kavuşturur, Ama başkaldıranlar kurak yerde oturur.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
Ey Tanrı, sen halkına öncülük ettiğinde, Çölde yürüdüğünde, (Sela)
8 Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Yer sarsıldı, Göklerden yağmur boşandı Tanrı'nın önünde, Sina Dağı sarsıldı Tanrı'nın, İsrail'in Tanrısı'nın önünde.
9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
Bol yağmurlar yağdırdın, ey Tanrı, Canlandırdın yorgun düşen yurdunu.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
Halkın oraya yerleşti, İyiliğinle mazlumların geçimini sağladın, ey Tanrı.
11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
Rab buyruk verdi, Büyük bir kadın topluluğu duyurdu müjdeyi:
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
“Kaçıyor, kaçıyor orduların kralları! Evi bekleyen kadınlar ganimeti paylaşıyor.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
Ağılların arasında uyurken, Kanatları gümüş, tüyleri pırıl pırıl altınla kaplı Bir güvercine benzersiniz.”
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
Her Şeye Gücü Yeten, kralları dağıtırken, Sanki Salmon Dağı'na kar yağıyordu.
15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
Ey Başan Dağı, Tanrı Dağı! Ey Başan Dağı, dorukları ulu dağ!
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
Ey ulu dağlar, niçin yan gözle bakıyorsunuz Tanrı'nın yerleşmek için seçtiği dağa? Evet, RAB orada sonsuza dek oturacaktır.
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
Tanrı'nın savaş arabaları sayısızdır, Rab kutsallık içinde Sina'dan geldi.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
Sen yükseğe çıktın, tutsakları peşine taktın, İnsanlardan, başkaldıranlardan bile armağanlar aldın, Oraya yerleşmek için, ya RAB Tanrı.
19 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
Her gün yükümüzü taşıyan Rab'be, Bizi kurtaran Tanrı'ya övgüler olsun. (Sela)
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
Tanrımız kurtarıcı bir Tanrı'dır, Ölümden kurtarış yalnız Egemen RAB'be özgüdür.
21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
Kuşkusuz Tanrı düşmanlarının başını, Suçlu yaşayanların kıllı kafasını ezer.
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
Rab, “Onları Başan'dan, Denizin derinliklerinden geri getireceğim” der,
23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
“Öyle ki, ayaklarını düşmanlarının kanına batırasın, Köpeklerinin dili de onlardan payını alsın.”
24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Ey Tanrı, senin zafer alayını, Tanrım'ın, Kralım'ın kutsal yere törenle gelişini gördüler:
25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
Başta okuyucular, arkada çalgıcılar, Ortada tef çalan genç kızlar.
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
“Ey sizler, İsrail soyundan gelenler, Toplantılarınızda Tanrı'ya, RAB'be övgüler sunun!”
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
Önde en küçük oymak Benyamin, Kalabalık halinde Yahuda önderleri, Zevulun ve Naftali önderleri oradalar!
28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
Ey Tanrı, Yeruşalim'deki tapınağından göster gücünü, Bizim için kullandığın gücünü, ey Tanrı. Krallar sana armağanlar sunacak.
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
Azarla kamışlar arasında yaşayan hayvanı, Halkların buzağılarıyla boğalar sürüsünü, Çiğne ayaklarınla gümüşe gönül verenleri, Dağıt savaştan zevk alan halkları!
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
Mısır'dan elçiler gelecek, Kûşlular ellerini Tanrı'ya doğru kaldırıverecek.
32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
Ey yeryüzünün krallıkları, Tanrı'ya ezgiler söyleyin, İlahilerle övün Rab'bi, (Sela)
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
Göklere, kadim göklere binmiş olanı. İşte sesiyle, güçlü sesiyle gürlüyor!
34 Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
Tanrı'nın gücünü tanıyın; O'nun yüceliği İsrail'in üzerinde, Gücü göklerdedir.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!
Ne heybetlisin, ey Tanrı, tapınağında! İsrail'in Tanrısı'na, Halkına güç, kudret veren Tanrı'ya övgüler olsun!

< Psalms 68 >