< Psalms 68 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
E KU iluna ke Akua, e hooauhee liilii i kona mau enemi: E auhee hoi imua ona ka poe i hoowahawaha ia ia.
2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Me he uahi la i puhiia'ku, pela e hoopuehu ai oe ia lakou; Me ka pilali i hehee ai imua o ke ahi, Pela e make ai ka poe hewa imua o ke Akua.
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
Aka, e olioli ka poe pono, e hauoli hoi imua o ke Akua; Oiaio, e hauoli loa lakou.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
E himeni aku oukou i ke Akua; E hoolea aku hoi i kona inoa: E hapai aku hoi i ka mea holokaa maluna o na lani, Ma koua inoa, o IA, a e hauoli imua ona.
5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
O ka Makua no ka poe makua ole, O ka Lunakanawai no na wahinekanemake, Oia ke Akua i kona wahi hoano e noho ai.
6 Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
Ua hoonoho ke Akua i na mea mehameha iloko o na ohana; O ka poe i paa i na kaula hao, kana i hoopuka mai nei; Aka, e noho no ka poe kipikipi ma kahi panoa.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
E ke Akua, i kou hele ana imua o kou poe kanaka, I kou eu ana'e iwaena o ka waonahele; (Sila)
8 Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Haalulu ae la ka honua, Hookulukulu mai la ka lani, ma ke alo o ke Akua: O Sinai hoi kekahi ma ke alo o ke Akua, ke Akua o Iseraela.
9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
Hoohelelei iho la oe, e ke Akua, i ka ua nui, I hoomau ai oe i kou hooilina i kona nawaliwali ana.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
Malaila i noho ai kou ekalesia; No kou maikai, e ke Akua, ua hoomakaukau oe no ka poe ilihune.
11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
Haawi mai la ka Haku i ka olelo; He lehulehu loa ka poe i hoolaha.
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
O na'lii o na poe kaua ua auhee wawe lakou: A o ka mea i noho ma ka hale ua puunaue no ia i ka waiwai pio.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
A i moe ae oukou mawaena o na ipuhao, E like auanei oukou me na eheu o ka manu ku i paapu i ke kala; A me kona mau hulu, i ke gula lenalena.
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
I ka wa i hoopuehu ai ka Mea mana loa i na'lii iloko ona, Ua like ia me ka hau ma Salemona;
15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
O ka mauna o ke Akua, ka mauna Basana: He mauna kiekie, ka mauna Basana.
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
O ke aha la ka oukou mea e kiei malu ai, e na maunakiekie? Eia ka mauna a ke Akua i makemake ai e noho, Oiaio, e noho mau loa o Iehova ma neia.
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
O na kaa o ke Akua elua umi tausani i papaluaia; O ka Haku ka iwaena o lakou, Pela ma Sinai, a ma kahi hoano.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
Ua pii ae oe iluna, ua lawe pio oe i ke pio ana; Ua loaa no ia oe na haawina no na kanaka, Oia, no ka poe kipikipi kekahi i noho pu mai ai ke Akua ka Haku.
19 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
E hoomaikaiia'ku ka Haku, ka mea i hooili ukana maluna o kakou i kela la i keia la, O ko kakou Akua e ola'i. (Sila)
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
O ko kakou Akua, oia ke Akua e ola'i; A no Iehova ka Haku ka puka ana ae no ka make.
21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
E hana pepe ke Akua i ke poo o kona poe enemi, A me ka pua lauoho o ka mea e hele ana'e ma kona mau hewa.
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
I mai la ke Akua, Mai Basana mai e alakai hou mai au; E hoihoi mai no hoi au mailoko mai o na hohonu o ke kai.
23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
I komo kou kapuwai iloko o ke koko o na enemi, A me ke alelo o kau mau ilio iloko o ia mea no.
24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Ua ike lakou i kou hele ana, e ke Akua, Na hele ana o ko'u Akua, kuu Alii, ma kahi hoano.
25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
Ua hele mua ae ka poe mele himeni, A mahope iho ka poe hookanikani i na kaula: A iwaena na kaikamahine e hookani timerela ana.
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
E hoomaikai aku oukou i ke Akua iloko o na auaina, A i ka Haku mai ke kumuwai o ka Iseraela.
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
Malaila o Beniamina ka mea uuku, o ko lakou alii kekahi, Na'lii o Iuda, ko lakou poe ahaolelo, Na'lii o Zebuluna, a me na'lii o Napetali.
28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
Ua kauoha mai kou Akua i kou ikaika: E hookupaa mai, e ke Akua, i ka mea au i hana'i no makou.
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
No kou luakini ma Ierusalema, E lawe ai na'lii i na makana ia oe.
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
E papa mai oe i ka holoholona o na ohe, Ke anaina o na mea ikaika, iwaena o na bipi o na lahuikanaka; A hoohaahaa iho kela keia ia ia iho me na apana kala: E hooauhee liilii oe i na kanaka puni kaua.
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
E hele mai na luna mailoko mai o Aigupita; E kikoo wawe aku o Aitiopa i kona mau lima i ke Akua.
32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
E oli aku i ke Akua, e na aupuni o ka honua, E himeni hoomaikai aku oukou i ka Haku; (Sila)
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
I ka mea e holokaa ana ma na lani o na lani kahiko; Aia, ke hoopuka mai la oia i kona leo, he leo mana.
34 Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
E haawi oukou no ke Akua ka mana; Maluna o ka Iseraela kona nani; O kona mana hoi, aia no i na ao.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!
He mea weliweli oe, e ke Akua, mailoko mai o kou wahi hoano: O ke Akua o ka Iseraela, oia ka mea i haawi mai i ka ikaika a me ka mana i kona poe kanaka. E hoomaikaiia'ku ke Akua.

< Psalms 68 >