< Psalms 68 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
Au maître-chantre. — Psaume de David. — Cantique. Que Dieu se lève, et ses ennemis seront dispersés; Ceux qui le haïssent fuiront devant sa face; ,
2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Comme la fumée se dissipe, tu les dissiperas; Comme la cire fond au feu, Ainsi périront les méchants devant Dieu.
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
Mais les justes se réjouiront; Ils triompheront en présence de Dieu; Ils seront transportés d'allégresse.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
Chantez à la gloire de Dieu, célébrez son nom. Préparez le chemin A celui dont le char s'avance à travers les plaines! L'Éternel est son nom; réjouissez-vous en sa présence!
5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
Il est le père des orphelins et le défenseur des veuves, Le Dieu qui réside dans sa demeure sainte.
6 Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
Dieu donne un foyer aux isolés; Il délivre les captifs et les met dans l'abondance; Mais les rebelles auront pour séjour le désert aride.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
Dieu, quand tu sortis à la tête de ton peuple, Quand tu t'avanças dans le désert. (Pause)
8 Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
La terre trembla, les cieux se fondirent devant Dieu; Le Sinaï même trembla devant Dieu, le Dieu d'Israël.
9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
Tu fis tomber, ô Dieu, une pluie de bienfaits sur ton héritage: Il était épuisé; tu restauras ses forces.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
Ton troupeau habita dans ce pays. Que dans ta bonté, ô Dieu, tu avais préparé pour le malheureux.
11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
Le Seigneur donne un ordre. Aussitôt les messagères de bonnes nouvelles Se réunissent en une troupe nombreuse.
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
Les rois des armées s'enfuient; ils s'enfuient. Et celle qui gardait la maison partage le butin.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
Tandis que vous reposez au milieu des bercails. Les ailes de la colombe se couvrent d'argent, Et son plumage de reflets d'or.
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
Quand le Tout-Puissant dispersa les rois, Il y eut sur le Tsalmon comme des flocons de neige.
15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
Montagnes de Dieu, montagnes de Basan, Montagnes aux cimes nombreuses, montagnes de Basan,
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
Montagnes aux cimes nombreuses, Pourquoi êtes-vous jalouses De la montagne que Dieu a choisie pour demeure? Oui, l'Éternel y demeurera toujours.
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
Les chars de Dieu se comptent par vingt mille. Par milliers de milliers. Le Seigneur vient du Sinaï dans son sanctuaire.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
Tu es monté sur la hauteur, tu as emmené des captifs; Tu as reçu les dons des hommes, même ceux des rebelles, Pour établir là ta demeure, ô Éternel Dieu!
19 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
Béni soit le Seigneur! Chaque jour il porte nos fardeaux, Le Dieu de notre salut. (Pause)
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
Dieu est pour nous le Dieu qui nous sauve; C'est l'Éternel, le Seigneur, qui délivre de la mort.
21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
Oui, Dieu écrasera la tête de ses ennemis. Le crâne chevelu de celui qui se plaît à marcher dans le crime.
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
Le Seigneur a dit: «De Basan je ramènerai mon peuple. Je le ramènerai des profondeurs de la mer,
23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
Afin que tu plonges tes pieds dans le sang, Et que la langue de tes chiens ait part Au carnage de l'ennemi!»
24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
On a vu ta marche, ô Dieu, La marche de mon Dieu, de mon Roi, dans le sanctuaire.
25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
En tête venaient les chanteurs; En arrière, les joueurs d'instruments; Au milieu, les jeunes filles battant du tambourin.
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
Bénissez Dieu dans vos assemblées; Bénissez le Seigneur, vous, descendants d'Israël!
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
Voici Benjamin, le plus jeune, qui marche en tête; Puis, les princes de Juda et leur troupe. Les princes de Zabulon et les princes de Nephthali.
28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
Ton Dieu a décrété ta puissance. Affermis, ô Dieu, ce que tu as fait pour nous,
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
Du haut de ton palais qui domine Jérusalem! Que les rois t'offrent des présents!
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
Tance la bête des roseaux, La troupe des taureaux Qu'entoure la multitude de leurs vassaux, Afin que tous se prosternent en t'offrant des lingots d'argent. Disperse les peuples qui veulent la guerre.
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
Les grands viendront de l'Egypte; L'Ethiopie s'empressera de tendre les mains vers Dieu.
32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
Royaumes de la terre, chantez un cantique à la gloire de Dieu! (Pause) Chantez en l'honneur du Seigneur,
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
En l'honneur de celui qui s'avance. Porté sur les cieux, les cieux éternels! Il fait retentir sa voix, sa voix puissante.
34 Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
Rendez hommage à Dieu! Sa majesté resplendit sur Israël; sa force éclate dans les nuées.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!
Dieu, du fond de tes sanctuaires, tu te rends redoutable! C'est lui, le Dieu d'Israël, Qui donne force et puissance à son peuple. Béni soit Dieu!

< Psalms 68 >