< Psalms 68 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
Přednímu z kantorů, Davidův žalm k zpívání. Povstane Bůh, a rozprchnou se nepřátelé jeho, a utekou od tváři jeho ti, kteříž ho mají v nenávisti.
2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Jakož rozehnán bývá dým, tak je rozženeš; jakož se rozplývá vosk před ohněm, tak bezbožní zahynou před tváří Boží.
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
Spravedliví pak veselíce se, poskakovati budou před Bohem, a plésati budou radostí.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
Prozpěvujte Bohu, žalmy zpívejte jménu jeho, vyrovnejte cestu tomu, kterýž se vznáší na oblacích. Hospodin jest jméno jeho, plésejtež před ním.
5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
Otec jest sirotků a ochránce vdov, Bůh v příbytku svatém svém.
6 Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
Bůh samotné rozmnožuje v domy, vyvodí vězně z okovů, zpurní pak bydliti musejí v zemi vyprahlé.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
Bože, když jsi předcházel lid svůj, když jsi kráčel po poušti, (Sélah)
8 Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Země se třásla, též i nebesa rozplývala se před tváří Boží, i ta hora Sinai před přítomností Boží, Boha Izraelského.
9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
Deštěm štědrosti hojné skropoval jsi, Bože, dědictví své, a když zemdlívalo, ty jsi je zase očerstvoval.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
Zástupové tvoji přebývají v něm, kteréžs ty nastrojil dobrotivostí svou pro chudého, ó Bože.
11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
Pán dal slovo své, i těch, kteréž potěšeně zvěstovaly, zástup veliký, řkoucích:
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
Králové s vojsky utíkali, utíkali, a doma hlídající dělily kořisti.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
Ačkoli jste mezi kotly ležeti musili, však jste jako holubice, mající křídla postříbřená, a brky z ryzího zlata.
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
Když Všemohoucí rozptýlí krále v této zemi, zbělíš jako sníh na hoře Salmon.
15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
Hoře veliké, hoře v Bázan, hoře pahrbkovaté, hoře v Bázan.
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
Pročež vyskakujete, hory pahrbkovaté? Na tétoť hoře zalíbilo se Bohu přebývati, jistě žeť na ní Hospodin na věky přebývati bude.
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
Vozů Božích jest dvadceti tisíců, mnoho tisíců andělů, Pán pak mezi nimi jako na Sinai v svatyni přebývá.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
Vstoupil jsi na výsost, jaté jsi vedl vězně, vzal jsi dary pro lidi. I nejzpurnější k přebývání s námi, Hospodine Bože, přivozuješ.
19 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
Požehnaný Pán, každého dne nás osýpá dary svými, Bůh silný spasení našeho. (Sélah)
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
Onť jest Bůh silný náš, Bůh silný k hojnému spasení. Hospodin Pán z smrti vyvodí.
21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
Raní zajisté Bůh hlavu nepřátel svých, a vrch hlavy vlasatý chodícího v hříších svých.
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
Řekltě Pán: Zaseť vyvedu své, jako z Bázan, zase vyvedu z hlubokosti mořské.
23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
A protož noha tvá zbrocena bude ve krvi, i jazyk psů tvých krví nepřátelskou.
24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Spatřili slavné jití tvé, Bože, jití silného Boha mého a krále mého v svatyni.
25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
Napřed šli zpěváci, z zadu hrající na nástroje hudebné, u prostřed pak děvečky bubnující.
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
V shromážděních dobrořečte Bohu Pánu, kteříž jste z národu Izraelského.
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
Tu ať jest Beniamin maličký, kterýž je opanoval, tu knížata z Judy a houfové jejich, knížata z Zabulona, i knížata z Neftalíma.
28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
Obdařil tě Bůh tvůj silou. Potvrdiž, Bože, což jsi mezi námi vzdělal,
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
Z chrámu svého nad Jeruzalémem, do něhož tobě přinášeti budou králové dary.
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
Zahub zástup kopidlníků, sebrání mocných vůdců i lidu bujného, pyšně vykračující s kusy stříbra; rozptyl lidi žádostivé válek.
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
Přijdouť nejvzácnější z Egypta, Mouřenínská země rychle vztáhne ruku svou k Bohu.
32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
Království země zpívejte Bohu, žalmy zpívejte Pánu, (Sélah)
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
Tomu, kterýž se vznáší nad nebem nebes starodávních; aj, vydává hlas svůj, hlas přemocný.
34 Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
Dejte čest síly Bohu, jehož důstojnost nad Izraelem, a velikomocnost jeho na oblacích.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!
Přehrozný jsi, ó Bože, z svatých příbytků svých. Bůh silný Izraelský, onť dává moc a sílu lidu svému, Bůh požehnaný.

< Psalms 68 >