< Psalms 68 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
POLO si Yuus ya ucajulo, polo y enimiguña ya ufanmachalapon: polo ayo sija y chumatlie güe ya ufanmalago gui menaña.
2 Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
Taegüije y manajanao y aso, taegüijeja yute sija: taegüije y maderite y danges gui menan guafe, taegüijeja manmalingoñija y manaelaye gui menan Yuus.
3 Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
Lao y manunas ufansénmagof: ufansenalegre gui menan Yuus: magajet ya usendangculo y minagofñija.
4 Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
Cantaye si Yuus, cantaye alabansa sija y naanña: nacajulo y chalan para ayo na maudae y inanaco y desierto sija; y naanña, si Yah ya fansenmagof gui menaña.
5 Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
Tatan y manaetata ya y jues para y manbiuda, si Yuus gui sinantos na sagaña.
6 Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
Si Yuus munafañaga y taeparientes gui familia sija: güiya chumule juyong preso para umegae: lao y managuaguat mañagaja gui anglo na tano.
7 Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
O Yuus, mientras unjanao gui menan y taotao; mientras na unfamocat gui inanaco desierto. (Sila)
8 Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Y tano mayeyengyong, y langet locue manutujo gui menan Yuus: ayo iya Sinae mayengyong gui menan Yuus, ni si Yuus guiya Israel.
9 Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
Jago, O Yuus, tumago megae na uchan, yan jago munafitme y erensiamo na taotao anae yayas.
10 Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
Y inetnon taotaomo mañaga güije: jago, O Yuus, fumamauleg y minaulegmo para y mamoble.
11 Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
Si Jeova jananae ni finijo: yan mandangculo ayo na inetnon famalaoan ni y munamatungo:
12 “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
Ray sija y inetnon sendalo falago chadig: ya güiya palaoan ni y sumasaga iya sija mafacae y inamot na güinaja.
13 Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
Yaguin manmalago jamyo dumescansa gui quelat quinilo; calang y papan y paluma nii platiao, yan y piluña nii amariyo calang oro.
14 Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
Anae ayo todo janasiña manafanmachalapon y ray sija guiya güiya: taegüije anae mamodong nieve guiya Salmón.
15 Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
Y egso Yuus y egso Basán: y gostaquilo na ogso y egso Basán.
16 Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
Sa jafa na manaatansegüet, jamyo nii manaquilo na osgo guato gui egso güinaeyan Yuus para sagaña: magajet na si Jeova sumaga güije para taejinecog.
17 Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
Y caretan Yuus y viente mil, junggan, miyares yan miyares ya si Jeova gui entaloñija taegüije iya Sinae, iya santos na sagaña.
18 Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
Jagasja jao cajulo iya jululo, jagas uncone y mamacautiba na megae: jagas unresibe ninae sija entre taotao sija: magajet entre y managuaguat locue, para si Jeova Yuus usiña sumaga gui entaloñija.
19 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
Bendito si, Jeova nii todo y jaane jaencatga y catgata, junggan, ayo y Yuus y satbasionta. (Sila)
20 Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
Si Yuus güiya si Yuus satbasion para jita: ya y jinanao guinin y finatae iyon Jeova, Señot.
21 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
Lao si Yuus janafanlamen y ilon y enimiguña yan y cácagong y manmipe ayo y sisigueja gui isaoña.
22 Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
Ya si Jeova ilegña: Bae chule talo guinin Basán, bae chule sija talo, guinin y tádodong na tase.
23 kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
Ya y adengmo siña umanaatunog gui jâgâ ya y jila y gamo galago siña patten y enimigumo.
24 Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
Sija jalie y jinanaomo, O Yuus; magajet y jinanao y Yuusso, Rayjo gui sinantos na sagaña.
25 Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
Y mangacanta manjajanao gui menan, y mandadangdang yan y dandanñija jatatituye; y entaloñija y donseya sija ni y mandadangdang nii pandireta.
26 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
Fanbendise si Yuus gui jalom y inetnon taotao; junggan, jamyo y tutujonña guiya Israel.
27 Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
Ayonae estaba y diquique as Benjamin y magasñija, y prinsipen Juda yan y compañia apapagat, y prinsipen Sabulon yan y prinsipen Neftali.
28 Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
Y Yuusmo tumago y minetgotmo; O Yuus, nametgot y chechomo para jame.
29 Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
Pot causa y templomo guiya Jerusalem, y ray sija manmañuñule ninae sija para jago.
30 Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
Lalatde y dadao na gâgâ gui piao, y manadan nobiyo yan y tatneron gataotao, nii guinocha papa adengñija y pedason salape sija: jochalapon ayosija taotao nii manmalago manguera.
31 Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
Ufanmato y prinsipe sija guinin Egipto: Etiopia guse ujaestira y canaeña gui as Yuus.
32 Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
Cantaye si Yuus jamyo nii raenon tano; O canta tinina para y Señot. (Sila)
33 Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
Para ayo y maudae gui jilo y langet y langet sija, nii guinin ampman na tiempo; estagüe na güiya masangan nii inagang; nii gaeninasiña na inagang.
34 Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
Sangan y minetgot Yuus: y minagasña gaegue gui jilo Israel, yan y minetgotña gaegue gui jalom y mapagages.
35 Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!
O Yuus, ninamaañaojao gui santos na sagamo sija: y Yuus Israel, güiya numae minetgot yan ninasiña y taotaoña: Bendito si Yuus.