< Psalms 67 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa kí ó sì bùkún fún wa, kí ó sì jẹ́ kí ojú rẹ̀ tàn yí wa ká,
Przewodnikowi chóru, na Neginot. Psalm i pieśń. Niech Bóg się zmiłuje nad nami i błogosławi nam, niech rozjaśni nad nami swoje oblicze. (Sela)
2 kí ọ̀nà rẹ le di mí mọ̀ ní ayé, ìgbàlà rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Aby poznano na ziemi twoją drogę, wśród wszystkich narodów twoje zbawienie.
3 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́!
Niech cię wysławiają ludy, o Boże, niech cię wysławiają wszystkie ludy.
4 Kí orílẹ̀-èdè kí ó yọ̀, kí ó sì kọrin fún ayọ̀, nítorí ìwọ fi òdodo darí àwọn ènìyàn, ìwọ sì jẹ ọba àwọn orílẹ̀-èdè ní ayé.
Niech narody się radują i wykrzykują, bo ty będziesz sądził ludy sprawiedliwie i rządzić będziesz narodami na ziemi. (Sela)
5 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́. (Sela)
Niech cię wysławiają ludy, o Boże, niech cię wysławiają wszystkie ludy.
6 Nígbà náà ní ilẹ̀ yóò mú ìkórè rẹ̀ wá, Ọlọ́run, Ọlọ́run wa, yóò bùkún fún wa.
[Wtedy] ziemia wyda swój plon i Bóg, nasz Bóg, będzie nam błogosławić.
7 Ọlọ́run yóò bùkún fún wa, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò sì máa bẹ̀rù rẹ̀.
Niech nam Bóg błogosławi i niech się go boją wszystkie krańce ziemi.

< Psalms 67 >