< Psalms 67 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa kí ó sì bùkún fún wa, kí ó sì jẹ́ kí ojú rẹ̀ tàn yí wa ká,
Przedniejszemu śpiewakowi na Neginot psalm ku śpiewaniu. Boże! zmiłuj się nad nami, a błogosław nam, rozświeć oblicze twoje nad nami. (Sela)
2 kí ọ̀nà rẹ le di mí mọ̀ ní ayé, ìgbàlà rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Aby tak poznali na ziemi drogę twoję, a po wszystkich narodach zbawienie twoje.
3 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́!
Tedy cię będą wysławiały narody o Boże! Będą cię wysławiać wszyscy ludzie!
4 Kí orílẹ̀-èdè kí ó yọ̀, kí ó sì kọrin fún ayọ̀, nítorí ìwọ fi òdodo darí àwọn ènìyàn, ìwọ sì jẹ ọba àwọn orílẹ̀-èdè ní ayé.
Radować się będą i wykrzykać narody; bo ty będziesz sądził ludzi w sprawiedliwości, a narody będziesz sprawował na ziemi. (Sela)
5 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́. (Sela)
Będą cię wysławiać narody, o Boże! Będą cię wysławiać wszyscy ludzie.
6 Nígbà náà ní ilẹ̀ yóò mú ìkórè rẹ̀ wá, Ọlọ́run, Ọlọ́run wa, yóò bùkún fún wa.
Ziemia także wyda urodzaj swój; niech nam błogosławi Bóg, Bóg nasz.
7 Ọlọ́run yóò bùkún fún wa, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò sì máa bẹ̀rù rẹ̀.
Niech nam błogosławi Bóg, a niech się go boją wszystkie kraje ziemi.

< Psalms 67 >