< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
För sångmästaren; en sång, en psalm. Höjen jubel till Gud, alla länder;
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
lovsjungen hans namns ära, given honom ära och pris.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Sägen till Gud: Huru underbara äro icke dina gärningar! För din stora makts skull visa dina fiender dig underdånighet.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Alla länder skola tillbedja och lovsjunga dig; de skola lovsjunga ditt namn. (Sela)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Kommen och sen vad Gud har gjort; underbara äro hans gärningar mot människors barn.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Han förvandlade havet till torrt land; till fots gingo de genom floden; då gladdes vi över honom.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Genom sin makt råder han evinnerligen, hans ögon giva akt på hedningarna; de gensträviga må icke förhäva sig. (Sela)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Prisen, I folk, vår Gud, och låten hans lov ljuda högt;
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
ty han har beskärt liv åt vår själ och har icke låtit vår fot vackla.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Ty väl prövade de oss, o Gud, du luttrade oss, såsom silver luttras;
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
du förde oss in i fängelse, du lade en tung börda på vår rygg;
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
du lät människor fara fram över vårt huvud, vi måste gå genom eld och vatten. Men du har fört oss ut och vederkvickt oss.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Så kommer jag då till ditt hus med brännoffer, jag vill infria mina löften till dig,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
dem till vilka mina låppar öppnade sig, och som min mun uttalade i min nöd.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Brännoffer av feta får vill jag frambära åt dig, med offerånga av vädurar; jag vill offra både tjurar och bockar. (Sela)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Kommen och hören, så vill jag förtälja för eder, I alla som frukten Gud, vad han har gjort mot min själ.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Till honom ropade jag med min mun, och lovsång var redan på min tunga.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Om jag hade förehaft något orätt i mitt hjärta, så skulle Herren icke höra mig.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Men Gud har hört mig, han har aktat på mitt bönerop.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Lovad vare Gud, som icke har förkastat min bön eller vänt ifrån mig sin nåd!

< Psalms 66 >