< Psalms 66 >
1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Para el músico jefe. Una canción. Un salmo. ¡Aclamad a Dios con alegría, toda la tierra!
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
¡Cantad a la gloria de su nombre! ¡Ofrezcan gloria y alabanza!
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Dile a Dios: “¡Cuán asombrosas son tus obras! Por la grandeza de tu poder, tus enemigos se someten a ti.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Toda la tierra te adorará, y te cantará; cantarán a tu nombre”. (Selah)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Venid y ved las hazañas de Dios. una obra impresionante en favor de los hijos de los hombres.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Convirtió el mar en tierra seca. Atravesaron el río a pie. Allí, nos regocijamos en él.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Él gobierna con su poderío para siempre. Sus ojos vigilan a las naciones. No dejes que los rebeldes se levanten contra él. (Selah)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
¡Alabad a nuestro Dios, pueblos! Haz que se escuche el sonido de su alabanza,
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
que preserva nuestra vida entre los vivos, y no permite que nuestros pies se muevan.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Porque tú, Dios, nos has puesto a prueba. Nos has refinado, como se refina la plata.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Nos has llevado a la cárcel. Has puesto una carga sobre nuestras espaldas.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Permitiste que los hombres pasaran por encima de nuestras cabezas. Pasamos por el fuego y por el agua, pero nos has traído al lugar de la abundancia.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Entraré en tu templo con holocaustos. Te pagaré mis votos,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
que mis labios prometieron, y mi boca hablaba, cuando estaba angustiado.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Te ofreceré holocaustos de animales gordos, con la ofrenda de carneros, Ofreceré toros con cabras. (Selah)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Venid a escuchar, todos los que teméis a Dios. Declararé lo que ha hecho por mi alma.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Le grité con la boca. Fue ensalzado con mi lengua.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Si yo acariciara el pecado en mi corazón, el Señor no habría escuchado.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Pero, ciertamente, Dios ha escuchado. Él ha escuchado la voz de mi oración.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Bendito sea Dios, que no ha rechazado mi oración, ni su amorosa bondad de mi parte.