< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Načelniku godbe, pesem in psalm. Ukajte Bogu, vsi zemljani.
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Prepevajte slavo njegovega imena; slavo pridevajte hvali njegovi.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Govorite Bogu: Kako čestitljiv si v delih svojih: zavoljo obilosti moči tvoje se ti lažnjivo udajajo sovražniki tvoji.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Vsi zemljani naj se ti klanjajo in ti prepevajo; prepevajo naj tvojemu imenu, presilno.
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Pridite in glejte dela Božja; čestitljiv je v dejanji proti sinovom človeškim.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Morje izpreminja v suho; reko so pregazile noge, tam smo radovali se v njem.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Z močjo svojo gospoduje vekomaj; oči njegove gledajo narode: kateri so uporni, naj se ne povišujejo preveč pri sebi!
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Blagoslavljajte Boga našega, ljudstva, in glas hvale njegove naj se razlega;
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
Kateri je dušo našo nazaj postavil v življenje, in ne pripusti, da omahnejo noge naše.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Potem, ko si nas izkušal, Bog, raztopil si nas, kakor se topi srebro.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Peljal si nas v samo mrežo; dél si nam podprsnico okolo ledja.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Storil si, da je sédel človek na glavo našo, šli smo skozi ogenj in skozi vodo; slednjič si nas pripeljal do té sitosti.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Sè žgalnimi darovi pojdem v hišo tvojo in opravim svoje obljube,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
Katere so izrekle odprte ustne moje, in govorila moja usta v stiski moji.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Žgalne darí tolstih ovnov bodem ti daroval s kadilom; pripravil vole s kozli, močno.
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Pridite, poslušajte, kateri koli se bojite Boga, da povem, kaj je storil duši moji.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Njega sem klical sè svojimi usti, in povišan sem bil za govore svojega jezika.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Ako bi se bil v krivico obrnil sè srcem svojim, Gospod bi ne bil slišal.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Ali vendar slišal je Bog, ozrl se v prošnje moje glas.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Blagoslovljen Bog, kateri ni zavrgel prošnje moje in mi ni odtegnil milosti svoje.

< Psalms 66 >