< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Mai marelui muzician, o cântare sau un psalm. Înălțați sunet de bucurie către Dumnezeu, tot pământul.
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Cântați onoarea numelui său, faceți glorioasă lauda lui.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Spuneți lui Dumnezeu: Ce înfricoșător ești tu în lucrările tale! Prin măreția puterii tale dușmanii tăi ți se vor supune.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Tot pământul ți se va închina și îți va cânta; ei vor cânta numelui tău. (Selah)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Veniți și vedeți lucrările lui Dumnezeu, el este înfricoșător în faptele lui față de fiii oamenilor.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
El a prefăcut marea în uscat, au trecut prin potop cu piciorul; acolo ne-am bucurat în el.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
El stăpânește prin puterea lui pentru totdeauna; ochii lui privesc națiunile, să nu se înalțe cei răzvrătiți. (Selah)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Binecuvântați pe Dumnezeul nostru, oamenilor, și faceți să fie auzită vocea laudei lui,
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
El care ține sufletul nostru în viață și nu lasă să se clatine picioarele noastre.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Căci tu, Dumnezeule, ne-ai încercat, ne-ai purificat, așa cum se purifică argintul.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Ne-ai adus în plasă; ai pus necaz peste coapsele noastre.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Ai făcut ca oamenii să călărească peste capetele noastre; am mers prin foc și prin apă, dar tu ne-ai adus într-un loc bogat.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Voi intra în casa ta cu ofrande arse, îmi voi împlini promisiunile față de tine,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
Pe care buzele mele le-au rostit și gura mea le-a vorbit, când am fost în necaz.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Îți voi aduce sacrificii arse de vite îngrășate, cu tămâia berbecilor; voi aduce tauri împreună cu țapi. (Selah)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Veniți și ascultați, voi toți care vă temeți de Dumnezeu și voi vesti ce a făcut el pentru sufletul meu.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Către el am strigat cu gura mea și el a fost preamărit cu limba mea.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Dacă iau aminte la nelegiuire în inima mea, Domnul nu mă va asculta.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Dar, într-adevăr, Dumnezeu m-a auzit; a dat atenție la vocea rugăciunii mele.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Binecuvântat fie Dumnezeu, care nu a respins rugăciunea mea, nici mila lui de la mine.

< Psalms 66 >