< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Przewodnikowi chóru. Pieśń i psalm. [Radośnie] wykrzykujcie Bogu, wszystkie ziemie;
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Wyśpiewujcie chwałę jego imienia, oddawajcie mu chwalebną cześć.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Powiedzcie Bogu: Jak straszliwe [są] twe dzieła! Z powodu twojej wielkiej mocy poddadzą się twoi wrogowie.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Cała ziemia odda ci pokłon i śpiewać ci będzie; śpiewać będzie twemu imieniu. (Sela)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Chodźcie, zobaczcie dzieła Boże, straszliwe są [jego] dzieła pośród synów ludzkich.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Zamienił morze [w] suchą [ziemię], pieszo przeszli przez rzekę; tam się nim weseliliśmy.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Panuje w swej mocy na wieki, jego oczy patrzą na narody, buntownicy nie wywyższą się. (Sela)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Błogosławcie, narody, naszego Boga i rozgłaszajcie jego chwałę.
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
Zachował przy życiu naszą duszę i nie dał się zachwiać naszej nodze.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Doświadczyłeś nas bowiem, Boże, wypróbowałeś nas ogniem, jak srebro jest oczyszczone.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Zaprowadziłeś nas w sidła, włożyłeś ucisk na nasze biodra.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Pozwoliłeś ludziom deptać nam po głowach, przeszliśmy przez ogień i wodę, ale nas wyprowadziłeś na [miejsce] obfitości.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
[Dlatego] wejdę do twego domu z całopaleniem [i] wypełnię śluby;
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
Które wyraziły moje wargi i wypowiedziały moje usta w utrapieniu.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Będę ci składał w ofierze całopalenia z tłustych zwierząt wraz z wonnością baranów, ofiaruję ci woły i kozły. (Sela)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Chodźcie, słuchajcie, wszyscy, którzy się boicie Boga, a opowiem, co uczynił dla mojej duszy.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Do niego wołałem moimi ustami i wychwalałem go moim językiem.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Gdybym zważał na nieprawość w swoim sercu, Pan by mnie nie wysłuchał.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
A jednak Bóg wysłuchał, przychylił się do głosu mojej modlitwy.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Błogosławiony Bóg, który nie odrzucił mojej modlitwy i nie [odebrał] mi swego miłosierdzia.

< Psalms 66 >