< Psalms 66 >
1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Az éneklőmesternek; zsoltár, ének. Örvendezz Istennek, oh te egész föld.
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Énekeljétek az ő nevének dicsőségét; dicsőítsétek az ő dicséretét!
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Mondjátok Istennek: Mily csudálatosak a te műveid: a te hatalmad nagy volta miatt hízelegnek néked ellenségeid.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Az egész föld leborul előtted; énekel néked, énekli a te nevedet. (Szela)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Jőjjetek és lássátok az Isten dolgait; csudálatosak az ő cselekedetei az emberek fiain.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
A tengert szárazzá változtatta, a folyamon gyalog mentek át: ott örvendeztünk ő benne.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
A ki uralkodik az ő hatalmával örökké, szemmel tartja a pogányokat, hogy az engedetlenek fel ne fuvalkodjanak magukban. (Szela)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Áldjátok népek a mi Istenünket, és hallassátok az ő dicséretének szavát.
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
A ki megeleveníti lelkünket, s nem engedi, hogy lábaink megtántorodjanak.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Mert megpróbáltál minket, oh Isten, megtisztítottál, a mint tisztítják az ezüstöt.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Hálóba vittél be minket, megszorítottad derekainkat.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Embert ültettél fejünkre, tűzbe-vízbe jutottunk: de kihoztál bennünket bőségre.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Elmegyek házadba égőáldozatokkal, lefizetem néked fogadásaimat,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
A melyeket ajakim igértek és szájam mondott nyomorúságomban.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Hízlalt juhokat áldozom néked égőáldozatul, kosok jóillatú áldozatával; ökröket bakokkal együtt áldozom néked. (Szela)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Jőjjetek el és halljátok meg, hadd beszélem el minden istenfélőnek: miket cselekedett az én lelkemmel!
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Hozzá kiálték az én szájammal, és magasztalás volt nyelvem alatt.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Ha hamisságra néztem volna szívemben, meg nem hallgatott volna az én Uram.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Ámde meghallgatott Isten, figyelmezett könyörgésem szavára.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Áldott az Isten, a ki nem vetette meg könyörgésemet, és kegyelmét nem vonta meg tőlem.