< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Rwĩmbo rwa Thaburi Anĩrĩrai Ngai mũkenete mũrĩ mbere ya Jehova, inyuĩ andũ othe a thĩ!
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Inai mũrahe riiri wa rĩĩtwa rĩake; gũkumio gwake tũmai kũgĩe na riiri!
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Ĩrai Ngai atĩrĩ, “Kaĩ ciĩko ciaku nĩ cia magegania-ĩ! Ũhoti waku nĩ mũnene mũno nginya ũgatũma thũ ciaku ciĩhetage nĩ guoya irĩ mbere yaku.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Andũ othe a thĩ nĩwe mainamagĩrĩra; mainaga magakũgooca, mainaga makagooca rĩĩtwa rĩaku.”
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Ũkai muone ũrĩa Ngai ekĩte, maũndũ marĩa ekagĩra andũ matikĩrĩ ma kũmakania!
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Aagarũrire iria rĩgĩtuĩka thĩ nyũmũ, nao andũ makĩhĩtũkĩra kũu maaĩ-inĩ na magũrũ; ũkai, tũmũkenere.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Nĩ ũndũ wa hinya wake, egũtũũra aathanaga nginya tene, maitho make maikaraga marorete ndũrĩrĩ, nĩguo andũ arĩa aremi matikagerie kũmũũkĩrĩra.
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Goocai Ngai witũ, inyuĩ andũ a ndũrĩrĩ, mũgambo wake wa kũmũgooca nĩũiguĩke;
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
nĩatũtũũrĩtie muoyo na akagirĩrĩria magũrũ maitũ matirũke.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Nĩgũkorwo Wee Ngai nĩũtũgeretie; ũtũtheragia ta ũrĩa betha ĩtheragio na mwaki.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Nĩwatũmire tũtwarwo njeera na ũgĩtũkuuithia mĩrigo mĩritũ.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Warekire andũ matũikarĩre mĩtwe; twagĩtuĩkanirie mwaki-inĩ o na maaĩ-inĩ, no ũgĩcooka ũgĩtũrehe kũndũ kũrĩ bũthi.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Nĩngũũka hekarũ-inĩ yaku ndĩ na maruta ma njino, nĩguo hingie mĩĩhĩtwa yakwa harĩwe,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
mĩĩhĩtwa ĩrĩa mĩromo yakwa yeranĩire, na ngĩmĩaria na kanua gakwa, rĩrĩa ndaarĩ thĩĩna-inĩ.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Ngũkũrutĩra igongona rĩa nyamũ iria noru, na ndute iruta rĩa ndũrũme; ngũkũrutĩra igongona rĩa ndegwa na mbũri.
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Ũkai mũthikĩrĩrie inyuothe arĩa mwĩtigĩrĩte Ngai; rekei ndĩmũhe ũhoro wa ũrĩa anjĩkĩire.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Ndamũkaĩire na kanua gakwa, ngĩmũgooca na rũrĩmĩ rwakwa.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Korwo ndaarĩ na mehia ngoro-inĩ yakwa-rĩ, Mwathani ndangĩanjiguire;
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
no ti-itherũ Ngai nĩathikĩrĩirie, na akĩigua mũgambo wakwa ngĩmũhooya.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Ngai arogoocwo, o we ũtaaregire kũigua ihooya rĩakwa, o na kana akĩaga kũnyonia wendo wake!

< Psalms 66 >