< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
Jusqu'à la Fin, psaume de la Résurrection. Terre, jette tout entière des cris de joie au Seigneur.
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Chantez des louanges en son nom; rendez gloire à sa louange;
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Dites à Dieu: Que tes œuvres sont redoutables, Seigneur! tes ennemis seront contraints, par la plénitude de ta puissance, à feindre devant toi.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Que toute la terre t'adore; qu'elle chante vers toi; qu'elle chante à ton nom.
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Venez et voyez les œuvres du Seigneur; il est redoutable en ses conseils, sur les fils des hommes.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Il change la mer en une plage aride; on traversera le fleuve à pied. Là nous nous réjouirons en lui,
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Qui en sa force est le maître de toute éternité. Ses yeux regardent les nations; que ceux qui l'irritent ne s'exaltent point en eux-mêmes.
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Nations, bénissez notre Dieu, et faites retentir la voix de sa louange.
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
C'est lui qui a vivifié mon âme, et qui n'a point permis que mes pieds soient ébranlés.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Tu nous as éprouvés, ô Dieu; tu nous as purifiés par le feu, comme l'argent.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Tu nous as conduits en un piège; tu as chargé nos épaules d'affliction.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Tu as fait monter des hommes sur nos têtes; nous avons passé à travers l'eau et le feu, et tu nous as amenés en un lieu de rafraîchissement.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
J'entrerai dans ta demeure avec des holocaustes; je te rendrai les vœux
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
Que mes lèvres ont proférés; et ma bouche a parlé en mon affliction.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Je t'offrirai des holocaustes pleins de moelle, avec de l'encens et des béliers; je te sacrifierai des bœufs et des chèvres.
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Ô vous qui craignez le Seigneur, vous tous écoutez, et je dirai que de grandes choses il a faites pour mon âme.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
J'ai crié vers lui de ma bouche; je l'ai glorifié de ma langue.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Si, en mon cœur, j'ai connu l'iniquité, que le Seigneur ne m'exauce jamais.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
A cause de cela, le Seigneur m'a écouté; il a été attentif à la voix de ma prière.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Béni soit Dieu qui n'a jamais rejeté ma prière et n'a point détourné de moi sa miséricorde.

< Psalms 66 >