< Psalms 66 >
1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
To the victorie, the song of salm.
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Al the erthe, make ye ioie hertli to God, seie ye salm to his name; yyue ye glorie to his heriyng.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Seie ye to God, Lord, thi werkis ben dredeful; in the multitude of thi vertu thin enemyes schulen lie to thee.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
God, al the erthe worschipe thee, and synge to thee; seie it salm to thi name.
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Come ye and se ye the werkis of God; ferdful in counseils on the sones of men.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Which turnede the see in to drie lond; in the flood thei schulen passe with foot, there we schulen be glad in hym.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Which is Lord in his vertu withouten ende, hise iyen biholden on folkis; thei that maken scharp be not enhaunsid in hem silf.
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Ye hethen men, blesse oure God; and make ye herd the vois of his preising.
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
That hath set my soule to lijf, and yaf not my feet in to stiryng.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
For thou, God, hast preued vs; thou hast examyned vs bi fier, as siluer is examyned.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Thou leddist vs in to a snare, thou puttidist tribulaciouns in oure bak;
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
thou settidist men on oure heedis. We passiden bi fier and water; and thou leddist vs out in to refreschyng.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
I schal entre in to thin hous in brent sacrifices; Y schal yelde to thee my vowis,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
which my lippis spaken distinctly. And my mouth spake in my tribulacioun;
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Y shal offre to thee brent sacrificis ful of merowy, with the brennyng of rammes; Y schal offre to thee oxis with buckis of geet.
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Alle ye that dreden God, come and here, and Y schal telle; hou grete thingis he hath do to my soule.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
I criede to hym with my mouth; and Y ioyede fulli vndir my tunge.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
If Y bihelde wickidnesse in myn herte; the Lord schal not here.
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Therfor God herde; and perseyuede the vois of my bisechyng.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Blessid be God; that remeued not my preyer, and `took not awei his merci fro me.