< Psalms 66 >

1 Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
За първия певец, псаломска песен. Възкликнете към Бога, всички земи,
2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
Възпейте славата на Неговото име, Като Го хвалите, хвалете Го славно.
3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
Речете Богу: Колко са страшни делата Ти! Поради величието на Твоята сила Даже враговете Ти ще се преструват пред Тебе за покорни.
4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
Цялата земя ще Ти се кланя и ще Те славослови, Ще славословят името Ти. (Села)
5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
Дойдете та вижте делата на Бога, Който страшно действува към човешките чада.
6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
Превърна морето в суша; Пеши преминаха през реката; Там се развеселиха в Него.
7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
Със силата Си господарува до века: Очите Му наблюдават народите; Бунтовниците нека не превъзнасят себе си. (Села)
8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
Вие племена благославяйте нашия Бог, И направете да се чуе гласът на хвалата Му,
9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
Който поддържа в живот душата ни. И не оставя да се клатят нозете ни.
10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
Защото Ти, Боже, си ни спасил, Изпитал си ни както се изпитва сребро.
11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
Въвел си ни в мрежата, Турил си тежък товар на гърба ни.
12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
Направил си да яздят човеци върху главите ни; Преминахме през огън и вода; Но Ти ни изведе на богато място.
13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
Ще вляза в дома Ти с всеизгаряния, Ще изпълня пред Тебе обреците,
14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
Които произнесоха устните ми И говориха устата ми в бедствието ми.
15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
Всеизгаряния от тлъсти овни ще Ти принеса с темян, Ще принеса волове и кози. (Села)
16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
Дойдете, слушайте, всички, които се боите от Бога, И ще разкажа онова, което е сторил на душата ми.
17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
Към него извиках с устата си; И Той ще бъде възвисен чрез езика ми.
18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
Ако в сърцето си бях гледал благоприятно на неправда, Господ не би послушал;
19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
Но Бог наистина послуша, Обърна внимание на гласа на молбата ми.
20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!
Благословен да е Бог. Който не отстрани от мене ни молитвата, ни Своята милост.

< Psalms 66 >