< Psalms 65 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Orin. Ìyìn ń dúró dè ọ́, Ọlọ́run, ní Sioni; sí ọ ni a ó mú ẹ̀jẹ́ wa ṣẹ.
Jusqu'à la Fin. Hymne de David, inspiré des paroles de Jérémie et Ezéchiel à l'époque de la déportation, et quand ils étaient sur le point de sortir. O Dieu, il convient en Sion de te chanter des hymnes; et des vœux te seront rendus.
2 Ìwọ tí ó ń gbọ́ àdúrà, gbogbo ènìyàn yóò sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
Exauce ma prière; toute chair ira à toi.
3 Ọ̀ràn àìṣedéédéé borí mi bí ó ṣe ti ìrékọjá wa ni! Ìwọ ni yóò wẹ̀ wọ́n nù kúrò.
Les paroles des méchants ont prévalu contre nous; mais tu nous pardonneras nos impiétés.
4 Ìbùkún ni fún àwọn tí o yàn tí o mú wa láti máa gbé àgọ́ rẹ! A tẹ́ wá lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere inú ilé rẹ, ti tẹmpili mímọ́ rẹ.
Heureux celui que tu auras élu et adopté; il habitera en tes parvis. Nous nous rassasierons des biens de ta demeure. Ton temple est saint; il est admirable en justice.
5 Ìwọ dá wa lóhùn pẹ̀lú ohun ìyanu ti òdodo, Ọlọ́run olùgbàlà wa, ẹni tí ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé gbogbo òpin ayé àti àwọn tí ó jìnnà nínú òkun,
Exauce-nous, ô Dieu notre Sauveur, espérance de toute la terre et de ceux qui sont au loin sur la mer.
6 ìwọ tí ó dá òkè nípa agbára rẹ, tí odi ara rẹ ní àmùrè agbára,
Par ta force tu as formé les monts; tu es revêtu de puissance.
7 ẹni tí ó mú rírú omi òkun dákẹ́, ríru ariwo omi wọn, àti ìdágìrì àwọn ènìyàn.
Tu ébranles l'abîme de la mer, et ses flots retentissent; et les nations seront troublées.
8 Àwọn tí ó ń gbé òkèrè bẹ̀rù, nítorí àmì rẹ wọ̀n-ọn-nì; ìwọ mú ìjáde òwúrọ̀ àti ti àṣálẹ́ yọ̀, ìwọ pè fún orin ayọ̀.
Et ceux qui demeurent aux confins de la terre seront saisis de crainte, à cause de tes signes; tu répandras la joie de l'Orient à l'Occident.
9 Ìwọ bẹ ayé wò, o sì bomirin; ìwọ mú un ọ̀rọ̀ púpọ̀. Odò Ọlọ́run kún fún omi láti pèsè ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ibẹ̀ ni ìwọ ti yàn án.
Tu as visité la terre, et tu l'as enivrée; tu as multiplié tes dons pour l'enrichir. Le fleuve de Dieu a été rempli d'eau; tu as préparé leur nourriture: voilà comment est fertilisée la terre.
10 Ìwọ fi bomirin sí aporo rẹ̀ ìwọ tẹ́ ògúlùtu rẹ̀; ìwọ fi òjò mú ilẹ̀ rẹ̀ rọ̀, o sì bùkún ọ̀gbìn rẹ̀.
Abreuve ses sillons, multiplie ses fruits; la récolte qui germe se réjouira de ses rosées.
11 Ìwọ fi oore rẹ dé ọdún ní adé, ọ̀rá ń kán ní ipa ọ̀nà rẹ.
Tu béniras le cercle des mois qui est la couronne de ta bonté, et tes champs seront remplis d'abondance.
12 Pápá tútù ní aginjù ń kan àwọn òkè kéékèèké fi ayọ̀ di ara wọn ní àmùrè.
Les montagnes du désert seront engraissées, et les collines seront revêtues d'allégresse.
13 Agbo ẹran ni a fi wọ pápá tútù náà ní aṣọ; àfonífojì ni a fi ọkà bò mọ́lẹ̀, wọ́n hó fún ayọ̀, wọ́n ń kọrin pẹ̀lú.
Les béliers du troupeau sont couverts de toison; les vallées regorgeront de froment; elles crieront, et chanteront un hymne au Seigneur.

< Psalms 65 >