< Psalms 64 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Gbóhùn mi, Ọlọ́run, bí mo ti ń sọ àròyé mi pa ọkàn mi mọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù àwọn ọ̀tá.
Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Wysłuchaj, o Boże, mego głosu, gdy się modlę; zachowaj moje życie od strachu przed wrogiem.
2 Pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú ọ̀pọ̀ igbe lọ́wọ́ ìrúkèrúdò oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Ukryj mnie przed tajemną radą złoczyńców, przed zgrają czyniących nieprawość;
3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà, wọ́n sì fa ọrun wọn le láti tafà wọn, àní ọ̀rọ̀ kíkorò.
Którzy naostrzyli swój język jak miecz, nałożyli swoje strzały, słowa jadowite;
4 Wọ́n tafà ní ìkọ̀kọ̀ sí àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀: wọ́n tafà si lójijì, wọn kò sì bẹ̀rù.
Aby strzelać z ukrycia w niewinnego; strzelają znienacka i nikogo się nie boją.
5 Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú, wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹkùn sílẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀ wọ́n wí pé, “Ta ni yóò rí wa?”
Utwierdzają się w złym zamiarze, zmawiają się, jak ukryć pułapki, i mówią: Któż je zobaczy?
6 Wọ́n gbìmọ̀ àìṣòdodo, wọ́n wí pé, “A wa ti parí èrò tí a gbà tán!” Lóòótọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.
Szukają nieprawości, starannie jej poszukują; ich wnętrze i serce są głębokie.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà; wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.
Ale Bóg wypuści na nich strzałę, nagle odniosą rany;
8 Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́n, gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.
Własny język doprowadzi ich do upadku; wszyscy, którzy ich zobaczą, uciekną.
9 Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rù wọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́run wọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.
I zlękną się wszyscy ludzie, będą opowiadali o dziele Boga i zrozumieją jego czyny.
10 Jẹ́ kí olódodo kí ó yọ̀ nínú Olúwa yóò sì rí ààbò nínú rẹ̀. Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ní ọkàn yóò máa yìn ín.
A sprawiedliwy będzie się weselić w PANU i będzie mu ufał; i będą się chlubili wszyscy prawego serca.

< Psalms 64 >