< Psalms 64 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Gbóhùn mi, Ọlọ́run, bí mo ti ń sọ àròyé mi pa ọkàn mi mọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù àwọn ọ̀tá.
Zwana, Nkulunkulu, ilizwi lami esikhalazweni sami, ulondoloze impilo yami ekwesabeni isitha.
2 Pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú ọ̀pọ̀ igbe lọ́wọ́ ìrúkèrúdò oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Ungifihle ecebeni elifihliweyo lababi, ekuxokozeleni kwabenzi bobubi,
3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà, wọ́n sì fa ọrun wọn le láti tafà wọn, àní ọ̀rọ̀ kíkorò.
abalola ulimi lwabo njengenkemba, bagobise umtshoko wabo, ngitsho amazwi ababayo,
4 Wọ́n tafà ní ìkọ̀kọ̀ sí àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀: wọ́n tafà si lójijì, wọn kò sì bẹ̀rù.
ukutshoka opheleleyo besekusithekeni; bahle bamtshoke, bengesabi.
5 Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú, wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹkùn sílẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀ wọ́n wí pé, “Ta ni yóò rí wa?”
Baziqinisa edabeni olubi, bekhuluma ngokuthiya, bathi: Ngubani ongayibona?
6 Wọ́n gbìmọ̀ àìṣòdodo, wọ́n wí pé, “A wa ti parí èrò tí a gbà tán!” Lóòótọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.
Badingisisa iziphambeko; silungile ngecebo elicetshwe ngobuqili; umcabango wangaphakathi womuntu kanye lenhliziyo kujulile.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà; wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.
Kodwa uNkulunkulu uzabatshoka ngomtshoko masinyane; bazalinyazwa.
8 Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́n, gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.
Njalo bazakwenza olwabo ulimi luwele phezu kwabo; bonke abababonayo bazabaleka.
9 Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rù wọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́run wọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.
Labo bonke abantu bazakwesaba, batshumayele isenzo sikaNkulunkulu, baqedisise umsebenzi wakhe.
10 Jẹ́ kí olódodo kí ó yọ̀ nínú Olúwa yóò sì rí ààbò nínú rẹ̀. Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ní ọkàn yóò máa yìn ín.
Olungileyo uzajabula eNkosini, aphephele kuyo; bonke abaqotho ngenhliziyo bazazincoma.