< Psalms 63 >

1 Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda. Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ, òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi, ara mi fà sí ọ, ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀ níbi tí kò sí omi.
Salmo de Davi, quando ele estava no deserto de Judá: Deus, tu [és] meu Deus. Eu te busco ao amanhecer; minha alma tem sede de ti, minha carne muito te deseja, em terra seca, cansativa, sem águas.
2 Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́, mo rí agbára àti ògo rẹ.
Para que eu te veja em teu santuário, para ver tua força e tua glória.
3 Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ, ètè mi yóò fògo fún ọ.
Porque tua bondade [é] melhor que a vida; meus lábios te louvarão.
4 Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.
Assim te bendirei em minha vida; por teu nome levantarei minhas mãos.
5 A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ; pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.
Minha alma será saciada, como que de gorduras e muita comida; e minha boca te louvará com lábios alegres,
6 Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi; èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.
Quando eu me lembrar de ti em minha cama; nas vigílias da noite meus pensamentos estarão em ti.
7 Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi, mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
Porque tu tens sido meu socorro; e à sombra de tuas asas cantarei de alegria.
8 Ọkàn mí fà sí ọ: ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.
Minha alma está apegada a ti; tua mão direita me sustenta.
9 Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun; wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
Porém aqueles que procuram assolar a minha alma irão para as profundezas da terra.
10 Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
Eles serão derrubados pela força da espada; serão repartidos entre raposas.
11 Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.
Mas o Rei se alegrará em Deus; todo o que por ele jurar se alegrará, porque a boca dos mentirosos será tapada.

< Psalms 63 >