< Psalms 63 >

1 Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda. Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ, òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi, ara mi fà sí ọ, ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀ níbi tí kò sí omi.
A psalm of David when was he in [the] wilderness of Judah. O God - [are] God my you I am seeking earnestly you it is thirsty for you - self my it longs for you flesh my in a land dry and weary not water.
2 Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́, mo rí agbára àti ògo rẹ.
Thus in the sanctuary I have seen you to see strength your and glory your.
3 Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ, ètè mi yóò fògo fún ọ.
For [is] good covenant loyalty your more than life lips my they will extol you.
4 Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.
Thus I will bless you in life my in name your I will lift up hands my.
5 A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ; pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.
Like fat and fatness it will be satisfied self my and lips of cries of joy it will praise [you] mouth my.
6 Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi; èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.
If I have remembered you on beds my in [the] night-watches I meditate on you.
7 Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi, mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
For you are a help of me and in [the] shadow of wings your I shout for joy.
8 Ọkàn mí fà sí ọ: ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.
It clings self my after you me it supports right [hand] your.
9 Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun; wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
And they to destruction they are seeking life my they will go in [the] lower parts of the earth.
10 Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
People will pour him over [the] hands of [the] sword [the] portion of foxes they will be.
11 Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.
And the king he will rejoice in God he will boast every [one who] swears an oath by him for it will be shut up [the] mouth of [those who] speak falsehood.

< Psalms 63 >