< Psalms 61 >
1 Fún adarí orin. Ohun èlò orin olókùn. Ti Dafidi. Gbọ́ ẹkún mi, Ọlọ́run; tẹ́tí sí àdúrà mi.
“For the leader of the music. To be sung upon stringed instruments. A psalm of David.” Hear my cry, O God! Attend to my prayer!
2 Láti òpin ayé wá ni èmi yóò pè ọ́, mo pè nígbà àyà mi ń ṣàárẹ̀; mú mi lọ sí ibi àpáta tí ó ga jù mí lọ.
From the extremity of the land I cry unto thee in deep sorrow of heart; Lead me to the rock that is high above me!
3 Nítorí ìwọ ti jẹ́ ibi ààbò mi, ilé ìṣọ́ agbára àwọn ọ̀tá.
For thou art my refuge, My strong tower against the enemy.
4 Mo ń lépa láti máa gbé nínú àgọ́ rẹ títí láé kí n sì rí ààbò níbi ìyẹ́ apá rẹ.
I shall dwell in thy tabernacle for ever; I will seek refuge under the covert of thy wings.
5 Nítorí ìwọ ti gbọ́ àwọn ẹ̀jẹ́ mi, Ọlọ́run; Ìwọ ti fún mi ní ogún àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ rẹ.
For thou, O God! wilt hear my vows, And give me the inheritance of those who fear thy name.
6 Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn, ọdún rẹ̀ fún ìrandíran.
O prolong the life of the king! May his years extend through many generations!
7 Kí ó máa jẹ ọba níwájú Ọlọ́run títí láé; pèsè àánú àti òtítọ́ rẹ tí yóò máa ṣe ìtọ́jú rẹ.
May he reign for ever before God! Grant that mercy and truth may preserve him!
8 Nígbà náà ni èmi ó máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ títí láé kí n san ẹ̀jẹ́ mi ní ojoojúmọ́.
So will I sing praise to thy name for ever; I will daily perform my vows.