< Psalms 61 >

1 Fún adarí orin. Ohun èlò orin olókùn. Ti Dafidi. Gbọ́ ẹkún mi, Ọlọ́run; tẹ́tí sí àdúrà mi.
“To the chief musician upon Neginah, by David.” Hear, O God, my entreaty; listen to my prayer.
2 Láti òpin ayé wá ni èmi yóò pè ọ́, mo pè nígbà àyà mi ń ṣàárẹ̀; mú mi lọ sí ibi àpáta tí ó ga jù mí lọ.
From the end of the earth will I call unto thee, when my heart is overwhelmed: lead me to the rock that is too high for me.
3 Nítorí ìwọ ti jẹ́ ibi ààbò mi, ilé ìṣọ́ agbára àwọn ọ̀tá.
For thou hast been a shelter unto me, a strong tower against the enemy.
4 Mo ń lépa láti máa gbé nínú àgọ́ rẹ títí láé kí n sì rí ààbò níbi ìyẹ́ apá rẹ.
Let me sojourn in thy tent to all eternity; let me be sheltered under the covert of thy wings. (Selah)
5 Nítorí ìwọ ti gbọ́ àwọn ẹ̀jẹ́ mi, Ọlọ́run; Ìwọ ti fún mi ní ogún àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ rẹ.
For thou, O God, hast truly listened to my vows: thou hast given back the heritage of those that fear thy name.
6 Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn, ọdún rẹ̀ fún ìrandíran.
Oh, add days unto the king's days: may his years be as of many generations.
7 Kí ó máa jẹ ọba níwájú Ọlọ́run títí láé; pèsè àánú àti òtítọ́ rẹ tí yóò máa ṣe ìtọ́jú rẹ.
May he abide for ever before God: ordain that kindness and truth may guard him.
8 Nígbà náà ni èmi ó máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ títí láé kí n san ẹ̀jẹ́ mi ní ojoojúmọ́.
So will I sing praise unto thy name for ever, that I may pay my vows day by day.

< Psalms 61 >