< Psalms 60 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
För sångmästaren, efter "Vittnesbördets lilja"; en sång, till att inläras; av David, när han var i fejd med Aram-Naharaim och Aram-Soba, och Joab kom tillbaka och slog edoméerna i Saltdalen, tolv tusen man. Gud, du har förkastat och förskingrat oss, du har varit vred; upprätta oss igen.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Du har kommit jorden att bäva och rämna; hela nu dess revor, ty den vacklar.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Du har låtit ditt folk se hårda ting, du har iskänkt åt oss rusande vin.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
Men åt dem som frukta dig gav du ett baner, dit de kunde samla sig för att undfly bågen. (Sela)
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
På det att dina vänner må varda räddade, må du giva seger med din högra hand och bönhöra oss.
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Gud har talat i sin helgedom: "Jag skall triumfera, jag skall utskifta Sikem och skall avmäta Suckots dal.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
Mitt är Gilead, och mitt är Manasse, Efraim är mitt huvuds värn, Juda min härskarstav;
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Moab är mitt tvagningskärl, på Edom kastar jag min sko; höj jubelrop till min ära, du filistéernas land."
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Vem skall föra mig till den fasta staden, vem leder mig till Edom?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Har icke du, o Gud, förkastat oss, så att du ej drager ut med våra härar, o Gud?
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Giv oss hjälp mot ovännen; ty människors hjälp är fåfänglighet.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
Med Gud kunna vi göra mäktiga ting; han skall förtrampa våra ovänner.

< Psalms 60 >