< Psalms 60 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
В конец, о изменитися хотящих, в столпописание Давиду, в научение: внегда сожже Средоречие Сирийское и Сирию Совалскую, и возвратися Иоав и порази Едома в дебри Солей дванадесять тысящ. Боже, отринул ны еси и низложил еси нас, разгневался еси и ущедрил еси нас.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Стрясл еси землю и смутил еси ю: изцели сокрушение ея, яко подвижеся.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Показал еси людем Твоим жестокая: напоил еси нас вином умиления.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
Дал еси боящымся Тебе знамение, еже убежати от лица лука.
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Яко да избавятся возлюбленнии Твои, спаси десницею Твоею и услыши мя.
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Бог возглагола во святем Своем: возрадуюся, и разделю Сикиму, и юдоль Жилищ размерю.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
Мой есть Галаад, и Мой есть Манассий, Ефрем крепость главы Моея, Иуда царь Мой.
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Моав коноб упования Моего: на Идумею простру сапог Мой: Мне иноплеменницы покоришася.
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Кто введет мя во град ограждения? Или кто наставит мя до Идумеи?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Не Ты ли, Боже, отринувый нас? И не изыдеши, Боже, в силах наших?
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Даждь нам помощь от скорби: и суетно спасение человеческо.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
О Бозе сотворим силу: и Той уничижит стужающыя нам.